< Psalms 12 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
Au chef des chantres, à l’octave. Psaume de David. Au secours, Seigneur, car il n’est plus d’homme pieux! Car la loyauté est bannie des fils d’Adam.
2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
On se parle avec fausseté l’un à l’autre, on parle d’une langue mielleuse, d’un cœur plein de duplicité.
3 Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
Que l’Eternel supprime toutes les langues mielleuses, les lèvres qui s’expriment avec arrogance,
4 tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
ceux qui disent: "Par notre langue nous triomphons, nos lèvres sont notre force: qui serait notre maître?"
5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
Devant l’oppression des humbles, les plaintes des pauvres. "A cette heure je me lève, dit le Seigneur, j’apporte le salut à celui qu’on entoure de pièges."
6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
Les paroles de l’Eternel sont des paroles pures; c’est de l’argent raffiné au creuset dans le sol, et qui est sept fois épuré.
7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
Toi, ô Seigneur, tu les protèges les justes, tu les défends à jamais contre cette engeance.
8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
Les méchants rôdent aux alentours, quand la vilenie domine parmi les hommes.

< Psalms 12 >