< Psalms 12 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
Au maître de chant. Sur l'octave. Chant de David. Sauve, Yahweh! car les hommes pieux s'en vont, les fidèles disparaissent d'entre les enfants des hommes.
2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
On se dit des mensonges les uns aux autres; on parle avec des lèvres flatteuses et un cœur double.
3 Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
Que Yahweh retranche toutes les lèvres flatteuses, la langue qui discourt avec jactance,
4 tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
ceux qui disent: " Par notre langue nous sommes forts; nous avons avec nous nos lèvres: qui serait notre maître? "
5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
" A cause de l'oppression des affligés, du gémissement des pauvres, je veux maintenant me lever, dit Yahweh; je leur apporterai le salut après lequel ils soupirent. "
6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
Les paroles de Yahweh sont des paroles pures, un argent fondu dans un creuset sur la terre, sept fois purifié.
7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
Toi, Yahweh, tu les garderas; tu les préserveras à jamais de cette génération.
8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
Autour d'eux les méchants se promènent avec arrogance: autant ils s'élèvent, autant seront humiliés les enfants des hommes.

< Psalms 12 >