< Psalms 12 >

1 Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́; olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.
To him that excelleth upon the eight tune. A Psalme of Dauid. Helpe Lord, for there is not a godly man left: for the faithfull are fayled from among the children of men.
2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀; ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.
They speake deceitfully euery one with his neighbour, flattering with their lips, and speake with a double heart.
3 Kí Olúwa kí ó gé ètè èké wọn àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu
The Lord cut off all flattering lippes, and the tongue that speaketh proude things:
4 tí ó wí pé, “Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa; àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?”
Which haue saide, With our tongue will we preuaile: our lippes are our owne: who is Lord ouer vs?
5 “Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní, Èmi yóò dìde nísinsin yìí,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn.”
Now for the oppression of the needy, and for the sighes of the poore, I will vp, sayeth the Lord, and will set at libertie him, whom the wicked hath snared.
6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù, gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀, tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.
The wordes of the Lord are pure wordes, as the siluer, tried in a fornace of earth, fined seuen folde.
7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́ kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.
Thou wilt keepe them, O Lord: thou wilt preserue him from this generation for euer.
8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.
The wicked walke on euery side: when they are exalted, it is a shame for the sonnes of men.

< Psalms 12 >