< Psalms 119 >

1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
ALEPH. BIENAVENTURADOS los perfectos de camino; los que andan en la ley de Jehová.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Bienaventurados los que guardan sus testimonios, y con todo el corazón le buscan:
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Pues no hacen iniquidad los que andan en sus caminos.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Tú encargaste que sean muy guardados tus mandamientos.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
¡Ojalá fuesen ordenados mis caminos á observar tus estatutos!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Entonces no sería yo avergonzado, cuando atendiese á todos tus mandamientos.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Te alabaré con rectitud de corazón, cuando aprendiere los juicios de tu justicia.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
Tus estatutos guardaré: no me dejes enteramente.
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
BETH ¿Con qué limpiará el joven su camino? Con guardar tu palabra.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Con todo mi corazón te he buscado: no me dejes divagar de tus mandamientos.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
En mi corazón he guardado tus dichos, para no pecar contra ti.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Bendito tú, oh Jehová: enséñame tus estatutos.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
Con mis labios he contado todos los juicios de tu boca.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
Heme gozado en el camino de tus testimonios, como sobre toda riqueza.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
En tus mandamientos meditaré, consideraré tus caminos.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Recrearéme en tus estatutos: no me olvidaré de tus palabras.
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
GIMEL. Haz bien á tu siervo; que viva y guarde tu palabra.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Abre mis ojos, y miraré las maravillas de tu ley.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Advenedizo soy yo en la tierra: no encubras de mí tus mandamientos.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Quebrantada está mi alma de desear tus juicios en todo tiempo.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Destruiste á los soberbios malditos, que se desvían de tus mandamientos.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Aparta de mí oprobio y menosprecio; porque tus testimonios he guardado.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Príncipes también se sentaron y hablaron contra mí: [mas] tu siervo meditaba en tus estatutos.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
Pues tus testimonios son mis deleites, [y] mis consejeros.
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
DALETH. Pegóse al polvo mi alma: vivifícame según tu palabra.
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Mis caminos [te] conté, y me has respondido: enséñame tus estatutos.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Hazme entender el camino de tus mandamientos, y hablaré de tus maravillas.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Deshácese mi alma de ansiedad: corrobórame según tu palabra.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Aparta de mí camino de mentira; y hazme la gracia de tu ley.
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
Escogí el camino de la verdad; he puesto tus juicios [delante de mí].
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Allegádome he á tus testimonios; oh Jehová, no me avergüences.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
Por el camino de tus mandamientos correré, cuando ensanchares mi corazón.
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
HE. Enséñame, oh Jehová, el camino de tus estatutos, y guardarélo hasta el fin.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Dame entendimiento, y guardaré tu ley; y la observaré de todo corazón.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Guíame por la senda de tus mandamientos; porque en ella tengo mi voluntad.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Inclina mi corazón á tus testimonios, y no á la avaricia.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Aparta mis ojos, que no vean la vanidad; avívame en tu camino.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Confirma tu palabra á tu siervo, que te teme.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Quita de mí el oprobio que he temido: porque buenos son tus juicios.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
He aquí yo he codiciado tus mandamientos: vivifícame en tu justicia.
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
VAU. Y venga á mí tu misericordia, oh Jehová; tu salud, conforme á tu dicho.
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Y daré por respuesta á mi avergonzador, que en tu palabra he confiado.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
Y no quites de mi boca en ningún tiempo la palabra de verdad; porque á tu juicio espero.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
Y guardaré tu ley siempre, por siglo de siglo.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
Y andaré en anchura, porque busqué tus mandamientos.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
Y hablaré de tus testimonios delante de los reyes, y no me avergonzaré.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
Y deleitaréme en tus mandamientos, que he amado.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
Alzaré asimismo mis manos á tus mandamientos, que amé; y meditaré en tus estatutos.
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
ZAIN. Acuérdate de la palabra [dada] á tu siervo, en la cual me has hecho esperar.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
Esta es mi consuelo en mi aflicción: porque tu dicho me ha vivificado.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
Los soberbios se burlaron mucho de mí: [mas] no me he apartado de tu ley.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Acordéme, oh Jehová, de tus juicios antiguos, y consoléme.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
Horror se apoderó de mí, á causa de los impíos que dejan tu ley.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Cánticos me fueron tus estatutos en la mansión de mis peregrinaciones.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
Acordéme en la noche de tu nombre, oh Jehová, y guardé tu ley.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
Esto tuve, porque guardaba tus mandamientos.
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
CHETH. Mi porción, oh Jehová, dije, será guardar tus palabras.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Tu presencia supliqué de todo corazón: ten misericordia de mí según tu palabra.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
Consideré mis caminos, y torné mis pies á tus testimonios.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Apresuréme, y no me retardé en guardar tus mandamientos.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Compañías de impíos me han robado: [mas] no me he olvidado de tu ley.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
A media noche me levantaba á alabarte sobre los juicios de tu justicia.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Compañero soy yo de todos los que te temieren y guardaren tus mandamientos.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
De tu misericordia, oh Jehová, está llena la tierra: enséñame tus estatutos.
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
TETH. Bien has hecho con tu siervo, oh Jehová, conforme á tu palabra.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Enséñame bondad de sentido y sabiduría; porque tus mandamientos he creído.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Antes que fuera yo humillado, descarriado andaba; mas ahora guardo tu palabra.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Bueno eres tú, y bienhechor: enséñame tus estatutos.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
Contra mí forjaron mentira los soberbios: [mas] yo guardaré de todo corazón tus mandamientos.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Engrasóse el corazón de ellos como sebo; mas yo en tu ley me he deleitado.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Bueno me es haber sido humillado, para que aprenda tus estatutos.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
Mejor me es la ley de tu boca, que millares de oro y plata.
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
JOD. Tus manos me hicieron y me formaron: hazme entender, y aprenderé tus mandamientos.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Los que te temen, me verán, y se alegrarán; porque en tu palabra he esperado.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Conozco, oh Jehová, que tus juicios son justicia, y que conforme á tu fidelidad me afligiste.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
Sea ahora tu misericordia para consolarme, conforme á lo que has dicho á tu siervo.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Vengan á mí tus misericordias, y viva; porque tu ley es mi deleite.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Sean avergonzados los soberbios, porque sin causa me han calumniado: yo empero, meditaré en tus mandamientos.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Tórnense á mí los que te temen y conocen tus testimonios.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Sea mi corazón íntegro en tus estatutos; porque no sea yo avergonzado.
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
CAPH. Desfallece mi alma por tu salud, esperando en tu palabra.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Desfallecieron mis ojos por tu palabra, diciendo: ¿Cuándo me consolarás?
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Porque estoy como el odre al humo; mas no he olvidado tus estatutos.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
¿Cuántos son los días de tu siervo? ¿cuándo harás juicio contra los que me persiguen?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Los soberbios me han cavado hoyos; mas no [obran] según tu ley.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Todos tus mandamientos son verdad: sin causa me persiguen; ayúdame.
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Casi me han echado por tierra: mas yo no he dejado tus mandamientos.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Vivifícame conforme á tu misericordia; y guardaré los testimonios de tu boca.
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
LAMED. Para siempre, oh Jehová, permanece tu palabra en los cielos.
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
Por generación y generación es tu verdad: tú afirmaste la tierra, y persevera.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
Por tu ordenación perseveran hasta hoy [las cosas criadas]; porque todas ellas te sirven.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Si tu ley no hubiese sido mis delicias, ya en mi aflicción hubiera perecido.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Nunca jamás me olvidaré de tus mandamientos; porque con ellos me has vivificado.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Tuyo soy yo, guárdame; porque he buscado tus mandamientos.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Los impíos me han aguardado para destruirme: [mas] yo entenderé en tus testimonios.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
A toda perfección he visto fin: ancho sobremanera es tu mandamiento.
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
MEM ¡Cuánto amo yo tu ley! todo el día es ella mi meditación.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Me has hecho más sabio que mis enemigos con tus mandamientos; porque me son eternos.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
Más que todos mis enseñadores he entendido: porque tus testimonios son mi meditación.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
Más que los viejos he entendido, porque he guardado tus mandamientos.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
De todo mal camino contuve mis pies, para guardar tu palabra.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
No me aparté de tus juicios; porque tú me enseñaste.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
¡Cuán dulces son á mi paladar tus palabras! más que la miel á mi boca.
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
De tus mandamientos he adquirido inteligencia: por tanto he aborrecido todo camino de mentira.
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
NUN. Lámpara es á mis pies tu palabra, y lumbrera á mi camino.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
Juré y ratifiqué el guardar los juicios de tu justicia.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Afligido estoy en gran manera: oh Jehová, vivifícame conforme á tu palabra.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Ruégote, oh Jehová, te sean agradables los sacrificios voluntarios de mi boca; y enséñame tus juicios.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
De continuo está mi alma en mi mano: mas no me he olvidado de tu ley.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Pusiéronme lazo los impíos: empero yo no me desvié de tus mandamientos.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
Por heredad he tomado tus testimonios para siempre; porque son el gozo de mi corazón.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
Mi corazón incliné á poner por obra tus estatutos de continuo, hasta el fin.
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
SAMECH. Los pensamientos vanos aborrezco; mas amo tu ley.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi escondedero y mi escudo eres tú: en tu palabra he esperado.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Apartaos de mí, malignos; pues yo guardaré los mandamientos de mi Dios.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Susténtame conforme á tu palabra, y viviré: y no me avergüences de mi esperanza.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Sostenme, y seré salvo; y deleitaréme siempre en tus estatutos.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Hollaste á todos los que se desvían de tus estatutos: porque mentira es su engaño.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Como escorias hiciste consumir á todos los impíos de la tierra: por tanto yo he amado tus testimonios.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Mi carne se ha extremecido por temor de ti; y de tus juicios tengo miedo.
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
AIN. Juicio y justicia he hecho; no me dejes á mis opresores.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Responde por tu siervo para bien: no me hagan violencia los soberbios.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Mis ojos desfallecieron por tu salud, y por el dicho de tu justicia.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Haz con tu siervo según tu misericordia, y enséñame tus estatutos.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Tu siervo soy yo, dame entendimiento; para que sepa tus testimonios.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Tiempo es de hacer, oh Jehová; disipado han tu ley.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
Por eso he amado tus mandamientos más que el oro, y más que oro muy puro.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
Por eso todos los mandamientos de todas las cosas estimé rectos: aborrecí todo camino de mentira.
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
PE. Maravillosos son tus testimonios: por tanto los ha guardado mi alma.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
El principio de tus palabras alumbra; hace entender á los simples.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
Mi boca abrí y suspiré; porque deseaba tus mandamientos.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Mírame, y ten misericordia de mí, como acostumbras con los que aman tu nombre.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Ordena mis pasos con tu palabra; y ninguna iniquidad se enseñoree de mí.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Redímeme de la violencia de los hombres; y guardaré tus mandamientos.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Haz que tu rostro resplandezca sobre tu siervo; y enséñame tus estatutos.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Ríos de agua descendieron de mis ojos, porque no guardaban tu ley.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
TZADDI. Justo eres tú, oh Jehová, y rectos tus juicios.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
Tus testimonios, [que] has recomendado, [son] rectos y muy fieles.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Mi celo me ha consumido; porque mis enemigos se olvidaron de tus palabras.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Sumamente acendrada es tu palabra; y la ama tu siervo.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Pequeño soy yo y desechado; [mas] no me he olvidado de tus mandamientos.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
Tu justicia es justicia eterna, y tu ley la verdad.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
Aflicción y angustia me hallaron: [mas] tus mandamientos fueron mis deleites.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
Justicia eterna son tus testimonios; dame entendimiento, y viviré.
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
COPH. Clamé con todo mi corazón; respóndeme, Jehová, y guardaré tus estatutos.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
A ti clamé; sálvame, y guardaré tus testimonios.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Anticipéme al alba, y clamé: esperé en tu palabra.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Previnieron mis ojos las vigilias de la noche, para meditar en tus dichos.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Oye mi voz conforme á tu misericordia; oh Jehová, vivifícame conforme á tu juicio.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Acercáronse á la maldad los que [me] persiguen; alejáronse de tu ley.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Cercano estás tú, oh Jehová; y todos tus mandamientos son verdad.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
Ya ha mucho que he entendido de tus mandamientos, que para siempre los fundaste.
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
RESH. Mira mi aflicción, y líbrame; porque de tu ley no me he olvidado.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Aboga mi causa, y redímeme: vivifícame con tu dicho.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
Lejos está de los impíos la salud; porque no buscan tus estatutos.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Muchas son tus misericordias, oh Jehová: vivifícame conforme á tus juicios.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Muchos son mis perseguidores y mis enemigos; [mas] de tus testimonios no me he apartado.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Veía á los prevaricadores, y carcomíame; porque no guardaban tus palabras.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Mira, oh Jehová, que amo tus mandamientos: vivifícame conforme á tu misericordia.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
El principio de tu palabra es verdad; y eterno [es] todo juicio de tu justicia.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
SIN. Príncipes me han perseguido sin causa; mas mi corazón tuvo temor de tus palabras.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Gózome yo en tu palabra, como el que halla muchos despojos.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
La mentira aborrezco y abomino: tu ley amo.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Siete veces al día te alabo sobre los juicios de tu justicia.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Mucha paz tienen los que aman tu ley; y no hay para ellos tropiezo.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
Tu salud he esperado, oh Jehová; y tus mandamientos he puesto por obra.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Mi alma ha guardado tus testimonios, y helos amado en gran manera.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
Guardado he tus mandamientos y tus testimonios; porque todos mis caminos están delante de ti.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
TAU. Acérquese mi clamor delante de ti, oh Jehová: dame entendimiento conforme á tu palabra.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Venga mi oración delante de ti: líbrame conforme á tu dicho.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Mis labios rebosarán alabanza, cuando me enseñares tus estatutos.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Hablará mi lengua tus dichos; porque todos tus mandamientos son justicia.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Sea tu mano en mi socorro; porque tus mandamientos he escogido.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
Deseado he tu salud, oh Jehová; y tu ley es mi delicia.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Viva mi alma y alábete; y tus juicios me ayuden.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Yo anduve errante como oveja extraviada; busca á tu siervo; porque no me he olvidado de tus mandamientos.

< Psalms 119 >