< Psalms 119 >

1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
Inmensamente felices son los de proceder intachable, Quienes andan en la Ley de Yavé.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Inmensamente felices son los que observan sus Testimonios, Los que lo buscan de todo corazón.
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Ellos tampoco cometen injusticia. Andan en los caminos de Él.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Tú nos ordenaste Que guardemos tus Preceptos con diligencia.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
¡Cómo anhelo que sean establecidos mis caminos, Para guardar tus Estatutos!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Entonces no sería yo avergonzado Cuando observe todos tus Mandamientos.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Te daré gracias con rectitud de corazón Cuando aprenda tus rectos juicios.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
Guardaré tus Estatutos. No me abandones completamente.
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
¿Cómo puede un joven guardar puro su camino? Al mantenerlo según tu Palabra.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Con todo mi corazón te he buscado. No permitas que me desvíe de tus Mandamientos.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
Tu Palabra atesoré en mi corazón Para no pecar contra Ti.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Bendito seas Tú, oh Yavé. Enséñame tus Estatutos.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
Con mis labios conté Todas las Ordenanzas de tu boca.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
Me he regocijado en el camino de tus Testimonios, Tanto como en todas [las] riquezas.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
Meditaré en tus Ordenanzas. Consideraré tus caminos.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Me deleitaré en tus Estatutos. No olvidaré tu Palabra.
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Concede beneficio a tu esclavo, Que yo viva y guarde tu Palabra.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Abre mis ojos, Para que yo vea las maravillas de tu Ley.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Soy un peregrino en la tierra. No encubras de mí tus Mandamientos.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Mi alma se quebranta con el anhelo De seguir tus Ordenanzas en todo tiempo.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Tú reprendes a los arrogantes. Son malditos los que se desvían de tus Mandamientos.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Aparta de mí el oprobio y el menosprecio, Porque he guardado tus Testimonios.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Aunque los magistrados se sienten Y hablen contra mí, Tu esclavo medita en tus Estatutos.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
Tus Testimonios son también mi deleite y mis consejeros.
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Postrada en el polvo está mi alma. Dame vida según tu Palabra.
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Te declaré mis caminos, Y me respondiste. Enséñame tus Estatutos.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Hazme entender la vía de tus Estatutos Para que yo medite en sus maravillas.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi vida se disuelve a causa de la tristeza. Fortaléceme según tu Palabra.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Aparta de mí el camino falso, Y con bondad concédeme tu Ley.
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
Escogí el camino fiel. Me enfrenté a tus Ordenanzas.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Me apegué a tus Testimonios, oh Yavé. No me entregues a la vergüenza.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
Correré por el camino de tus Mandamientos, Porque Tú ensancharás mi corazón.
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
Enséñame, oh Yavé, la vía de tus Estatutos, Y lo guardaré hasta el fin.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Dame entendimiento para que yo observe tu Ley, Y la observaré de todo corazón.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Hazme andar por la senda de sus Mandamientos, Porque en ella me deleito.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Inclina mi corazón a tus Testimonios, Y no a ganancia deshonesta.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Aparta mis ojos para que no miren vanidad. Revíveme en tus caminos.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Establece tu Palabra para tu esclavo, Como la que produce reverencia a Ti.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Aleja de mí la reprobación que temo, Porque tus Ordenanzas son buenas.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
Mira, yo anhelo tus Preceptos. Revíveme en tu justicia.
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Venga a mí, oh Yavé, tu misericordia, Tu salvación, conforme a tu Palabra,
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
A fin de que tenga respuesta para el que me reprueba, Porque confío en tu Palabra.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
No quites de mi boca en algún momento la Palabra de verdad, Porque yo confío en tus Ordenanzas.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
Así observaré tu Ley continuamente, Eternamente y para siempre.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
Andaré en libertad, Porque busco tus Preceptos.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
Delante de reyes hablaré también de tus Testimonios, Y no me avergonzaré.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
Me deleitaré en tus Mandamientos, Los cuales amo.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
Alzaré mis manos hacia tus Mandamientos, Los cuales amo, Y meditaré en tus Estatutos.
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
Recuerda la promesa [dada] a tu esclavo, En la cual me ordenaste esperar.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
Ella es mi consuelo en mi aflicción, Porque tu Palabra me da vida.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
Muchos se burlan de mí, Pero no me apartan de tu Ley.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Recuerdo tus antiguas Ordenanzas, oh Yavé, Y me consuelo.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
Indignación ardiente se apoderó de mí A causa de los perversos que abandonan tu Ley.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Tus Estatutos fueron cantos para mí En la casa de mi peregrinaje.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
Recuerdo tu Nombre en la noche, oh Yavé, Y observo tu Ley.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
Esto me sucedió Para que yo observe tus Preceptos.
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi posesión es Yavé. Prometí que observaré tus Palabras.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Busqué tu favor con todo mi corazón. Sé bondadoso conmigo, según tu Palabra.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
Consideré mis caminos Y volví mis pies a tus Testimonios.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Me apresuré, no me demoré En guardar tus Mandamientos.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Las cuerdas de los perversos me rodearon, Pero no olvidé tu Ley.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
A medianoche me levanto Para darte gracias por tus justas Ordenanzas.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Soy compañero de todos los que te temen, Y de los que observan sus Preceptos.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
Oh Yavé, la tierra está llena de tu misericordia. Enséñame tus Estatutos.
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
Oh Yavé, bien hiciste a tu esclavo según tu Palabra.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Enséñame buen discernimiento y conocimiento, Porque creo tus Mandamientos.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Antes de ser afligido me extravié, Pero ahora observo tu Palabra.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Bueno eres Tú Y haces lo bueno. Enséñame tus Estatutos.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
Los arrogantes forjaron mentira contra mí. Yo observo tus Preceptos de todo corazón.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Los corazones de ellos están cubiertos de grasa. Yo me deleito en tu Ley.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Fue bueno para mí que fui afligido, Para que aprenda tus Estatutos.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
Mejor me es la Ley de tu boca Que millares de oro y plata.
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
Tus manos me hicieron y me afirmaron. Dame entendimiento para que aprenda tus Mandamientos.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Que los que te reverencian Me vean y se alegren, Porque confié en tu Palabra.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Sé, oh Yavé, que tus juicios con justos, Y que me afligiste según tu fidelidad.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
Oh, que tu misericordia me consuele, Conforme prometiste a tu esclavo.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Que tu compasión venga a mí, Para que yo viva, Porque tu Ley es mi deleite.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Sean avergonzados los arrogantes, Porque sin causa me calumnian, Pero yo meditaré en tus Preceptos.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Que se vuelvan a mí los que te temen, Los que conocen tus Testimonios.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Sea mi corazón íntegro en tus Estatutos, Para que no sea avergonzado.
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi alma desfallece por tu salvación. Pero confío en tu Palabra.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Se consumen mis ojos [esperando] tu Palabra, Mientras digo: ¿Cuándo me consolará?
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Aunque soy como odre en el humo, No olvido tus Estatutos.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
¿Cuántos son los días de tu esclavo? ¿Cuándo juzgarás a los que me persiguen?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Los arrogantes me cavaron fosa, Los que no concuerdan con tu Ley.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Todos tus Mandamientos son fieles. Me persiguen con engaño. Ayúdame.
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Casi me destruyen en la tierra, Pero yo no abandono tus Preceptos.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Vivifícame según tu misericordia, Y observaré los Testimonios de tu boca.
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
Para siempre, oh Yavé, Tu Palabra permanece en el cielo.
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
Por todas las generaciones es tu fidelidad. Tú estableciste la tierra, y permanece.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
Por tu mandato subsisten hasta hoy [todas las cosas], Porque todas ellas te sirven como esclavas.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Si tu Ley no fuera mi deleite, Entonces habría perecido en mi aflicción.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Jamás olvido tus Preceptos, Porque con ellos me vivificaste.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Tuyo soy. ¡Sálvame! Porque busqué tus Preceptos.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Me esperan los perversos para destruirme. Pero yo considero tus Testimonios.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
En toda perfección he visto límite. Tu Mandamiento es inmensamente amplio.
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
¡Oh, cuánto amo yo tu Ley! Todo el día es mi meditación.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Tus Mandamientos me hacen más sabio que mis enemigos, Porque siempre están conmigo.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
Tengo mejor entendimiento que todos mis maestros, Porque tus Testimonios son mi meditación.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
Entiendo más que los ancianos, Porque observo tus Preceptos.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
De todo mal camino contuve mis pies, Para observar tu Palabra.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
No me aparté de tus Ordenanzas, Porque Tú mismo me enseñaste.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
¡Cuán dulces son tus Palabras a mi paladar, Más que miel a mi boca!
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
De sus Preceptos recibo entendimiento, Por tanto aborrezco todo camino falso.
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
Lámpara a mis pies es tu Palabra, Y lumbrera a mi camino.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
Juré observar tus justas Ordenanzas. Lo cumpliré Y lo confirmo: Guardaré tus justas Ordenanzas.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Estoy afligido en gran manera. Oh Yavé, vivifícame según tu Palabra.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Acepta las ofrendas voluntarias de mi boca, oh Yavé, Y enséñame tus Ordenanzas.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Mi vida está de continuo en peligro, Pero yo no olvido tu Ley.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Los perversos me tienden una trampa, Pero yo no me desvío de tus Preceptos.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
Tus Testimonios son mi herencia eterna, Porque ellos son el gozo de mi corazón.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
Incliné mi corazón a cumplir tus Estatutos, De continuo hasta el fin.
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
Aborrezco a los de doble ánimo, Pero amo tu Ley.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Tú eres mi Refugio y mi Escudo. Confío en tu Palabra.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Apártense de mí, perversos, Para que yo observe los Mandamientos de mi ʼElohim.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Susténtame según tu Palabra para que viva Y no dejes que sea avergonzado de mi esperanza.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Susténtame para que sea salvo, Para que yo observe de continuo tus Estatutos.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Rechazas a todos los que se desvían de tus Estatutos, Porque su astucia es falsedad.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Removiste de la tierra [como] escoria a todos los perversos. Por tanto, amo tus Testimonios.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Mi carne se estremece de temor a Ti, Y ante tus juicios me lleno de pavor.
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
Actué con justicia y rectitud. No me abandones a mis opresores.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Sé garante de tu esclavo para bien, Que no me opriman los arrogantes.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Mis ojos desfallecen por tu salvación, Y por la Palabra de tu justicia.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Haz con tu esclavo según tu misericordia, Y enséñame tus Estatutos.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Yo soy tu esclavo. Dame entendimiento para comprender tus Testimonios.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Es tiempo de actuar, oh Yavé. Porque invalidaron tu Ley.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
Por tanto amo tus Mandamientos Más que el oro, sí, más que el oro fino.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
Por tanto estimo rectos todos tus Preceptos Con respecto a todas las cosas. Aborrezco todo camino falso.
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
¡Maravillosos son tus Testimonios! Por tanto los observa mi alma.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
La exposición de tus Palabras alumbra. Da entendimiento a los simples.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
Abrí bien mi boca y suspiré, Porque anhelaba tus Mandamientos.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Mírame y ten misericordia de mí, Como acostumbras con los que aman tu Nombre.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Afirma mis pasos con tu Palabra, Y no permitas que alguna iniquidad me domine.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Líbrame de la violencia de los hombres, Y observaré tus Mandamientos.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Haz resplandecer tu rostro sobre tu esclavo, Y enséñame tus Estatutos.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Manantiales de agua bajarán de mis ojos, Porque ellos no observan tu Ley.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
Justo eres Tú, oh Yavé, Y rectos son tus juicios.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
Tus Testimonios nos mandaste con justicia, Y extraordinaria fidelidad.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Mi celo me consume, Porque mis adversarios olvidaron tus Palabras.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Tu Palabra es muy pura, Por tanto, tu esclavo la ama.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Soy pequeño y despreciado, [Pero] no olvido tus Preceptos.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
Tu justicia es eterna, Y tu Ley es verdad.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
La aflicción y la angustia me alcanzaron, [Pero] tus Mandamientos son mi delicia.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
Tus Testimonios son justicia eterna. Dame entendimiento para que viva.
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Clamo con todo mi corazón. Respóndeme, oh Yavé. Observaré tus Estatutos.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
A Ti clamo: ¡Sálvame! Y observaré tus Testimonios.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Me levanté antes del alba y clamé. Espero tu Palabra.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mis ojos se anticipan a las vigilias de la noche Para meditar en tu Palabra.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Oye mi voz según tu misericordia. Vivifícame, oh Yavé, según tus Ordenanzas.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Los que siguen la perversidad se acercan. Están lejos de tu Ley.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Tú, oh Yavé, estás cerca, Y todos tus Mandamientos son verdad.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
Desde antaño conocí tus Testimonios, Que Tú estableciste para siempre.
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
Mira mi aflicción y rescátame, Porque yo no olvido tu Ley.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Defiende mi causa y redímeme, Vivifícame según tu Palabra.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
Lejos de los perversos está la salvación, Porque no buscan tus Estatutos.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Oh Yavé, grandes son tus misericordias. Vivifícame según tus Ordenanzas.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Muchos son mis perseguidores y mis adversarios, [Pero] yo no me aparto de tus Testimonios.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Veo a los traidores y me disgusto, Porque ellos no observan tu Palabra.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Considera cuánto amo tus Preceptos. Vivifícame, oh Yavé, según tu misericordia.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
La suma de tu Palabra es verdad, Y eterna cada una de tus justas Ordenanzas.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Príncipes me persiguen sin causa, Pero mi corazón tiene temor a tus Palabras.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Me regocijo en tu Palabra Como el que halla gran despojo.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
Aborrezco y repugno la mentira. Amo tu Ley.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Siete veces al día te alabo A causa de tus justas Ordenanzas.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Mucha paz tienen los que aman su Ley, Y no hay tropiezo para ellos.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
Oh Yavé, espero tu salvación Y practico tus Mandamientos.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Mi alma observa tus Testimonios, Y los ama intensamente.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
Observo tus Preceptos y tus Testimonios, Porque todos mis caminos están delante de Ti.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Llegue mi clamor ante Ti, oh Yavé. Dame entendimiento según tu Palabra.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Llegue mi súplica ante Ti. Líbrame según tu Palabra.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Mis labios rebozan alabanza Cuando Tú me enseñas tus Estatutos.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Hablará mi lengua tu Palabra, Porque todos tus Mandamientos son justicia.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Esté tu mano lista para socorrerme, Porque escogí tus Ordenanzas.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
Anhelo tu salvación, oh Yavé, Y tu Ley es mi deleite.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Viva mi alma y te alabe, Y que me ayuden tus Ordenanzas.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Anduve errante como oveja perdida. Busca a tu esclavo, Porque no olvido tus Mandamientos.

< Psalms 119 >