< Psalms 119 >
1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
ALEPH Bienaventurados aquellos cuyos caminos son irreprochables, que caminan según la ley de Yahvé.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Bienaventurados los que guardan sus estatutos, que lo buscan con todo su corazón.
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Sí, no hacen nada malo. Caminan por sus caminos.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Tú has ordenado tus preceptos, que debemos obedecer plenamente.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
Oh, si mis caminos fueran firmes ¡para obedecer tus estatutos!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Entonces no me decepcionaría, cuando considero todos tus mandamientos.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Te daré gracias con rectitud de corazón, cuando me entere de tus justos juicios.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
Observaré tus estatutos. No me abandones del todo. BETH
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
¿Cómo puede un joven mantener su camino puro? Viviendo según tu palabra.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Con todo mi corazón te he buscado. No dejes que me desvíe de tus mandamientos.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
He escondido tu palabra en mi corazón, para no pecar contra ti.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Bendito seas, Yahvé. Enséñame tus estatutos.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
Con mis labios, He declarado todas las ordenanzas de tu boca.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
Me he alegrado en el camino de tus testimonios, tanto como en todas las riquezas.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
Meditaré en tus preceptos, y considera tus caminos.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Me deleitaré en tus estatutos. No olvidaré tu palabra. GIMEL
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Haz el bien a tu siervo. Viviré y obedeceré tu palabra.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Abre mis ojos, para que pueda ver las maravillas de tu ley.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Soy un extranjero en la tierra. No me ocultes tus mandamientos.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Mi alma se consume de anhelo por tus ordenanzas en todo momento.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Has reprendido a los soberbios que están malditos, que se alejan de tus mandamientos.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Aleja de mí el reproche y el desprecio, porque he guardado tus estatutos.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Aunque los príncipes se sienten y me calumnien, tu siervo meditará en tus estatutos.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
En verdad, tus estatutos son mi deleite, y mis consejeros. DALETH
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi alma está postrada en el polvo. ¡Revívelo según tu palabra!
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Yo declaré mis caminos, y tú me respondiste. Enséñame tus estatutos.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
¡Déjame entender la enseñanza de tus preceptos! Entonces meditaré en tus maravillosas obras.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi alma está fatigada por el dolor; fortaléceme según tu palabra.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Guárdame del camino del engaño. ¡Concédeme tu ley graciosamente!
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
He elegido el camino de la verdad. He puesto tus ordenanzas delante de mí.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Me aferro a tus estatutos, Yahvé. No dejes que me decepcione.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
Yo corro por la senda de tus mandamientos, porque has liberado mi corazón. HE
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
Enséñame, Yahvé, el camino de tus estatutos. Los mantendré hasta el final.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Dame entendimiento y cumpliré tu ley. Sí, lo obedeceré con todo mi corazón.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Dirígeme por el camino de tus mandamientos, porque me deleito en ellos.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Vuelve mi corazón hacia tus estatutos, no hacia la ganancia egoísta.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Aparta mis ojos de mirar cosas sin valor. Revísame en tus caminos.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Cumple tu promesa a tu siervo, para que seas temido.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Quita mi desgracia que temo, porque tus ordenanzas son buenas.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
¡He aquí que anhelo tus preceptos! Revísame en tu justicia. VAV
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Que tu bondad amorosa también venga a mí, Yahvé, tu salvación, según tu palabra.
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Así tendré una respuesta para el que me reprocha, porque confío en tu palabra.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
No arrebates la palabra de la verdad de mi boca, porque pongo mi esperanza en tus ordenanzas.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
Así que obedeceré tu ley continuamente, por siempre y para siempre.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
Caminaré en libertad, porque he buscado tus preceptos.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
También hablaré de tus estatutos ante los reyes, y no se sentirá decepcionado.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
Me deleitaré en tus mandamientos, porque me encantan.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
Extiendo mis manos por tus mandamientos, que amo. Meditaré en tus estatutos. ZAYIN
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
Recuerda tu palabra a tu siervo, porque me diste esperanza.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
Este es mi consuelo en mi aflicción, porque tu palabra me ha revivido.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
Los arrogantes se burlan en exceso de mí, pero no me desvío de su ley.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Me acuerdo de tus ordenanzas de antaño, Yahvé, y me he consolado.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
La indignación se ha apoderado de mí, a causa de los impíos que abandonan tu ley.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Tus estatutos han sido mis canciones en la casa donde vivo.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
He recordado tu nombre, Yahvé, en la noche, y obedezco tu ley.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
Este es mi camino, que guarde tus preceptos. HETH
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Yahvé es mi porción. Prometí obedecer tus palabras.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
He buscado tu favor con todo mi corazón. Sé misericordioso conmigo según tu palabra.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
Consideré mis formas, y he dirigido mis pasos hacia tus estatutos.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Me apresuraré y no me retrasaré, para obedecer tus mandamientos.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Las cuerdas de los malvados me atan, pero no olvidaré su ley.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
A medianoche me levantaré para darte gracias, a causa de tus justas ordenanzas.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Soy amigo de todos los que te temen, de los que observan tus preceptos.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
La tierra está llena de tu amorosa bondad, Yahvé. Enséñame tus estatutos. TETH
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
Has tratado bien a tu siervo, según tu palabra, Yahvé.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Enséñame el buen juicio y el conocimiento, porque creo en tus mandamientos.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Antes de ser afligido, me extravié; pero ahora observo tu palabra.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Tú eres bueno y haces el bien. Enséñame tus estatutos.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
Los orgullosos me han untado con una mentira. Con todo mi corazón, guardaré tus preceptos.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Su corazón es tan insensible como la grasa, pero me deleito en tu ley.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Es bueno para mí que haya sido afligido, para que pueda aprender tus estatutos.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
La ley de tu boca es mejor para mí que miles de piezas de oro y plata. YODH
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
Tus manos me han hecho y me han formado. Dame entendimiento, para que aprenda tus mandamientos.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Los que te temen me verán y se alegrarán, porque he puesto mi esperanza en tu palabra.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Yahvé, sé que tus juicios son justos, que con fidelidad me has afligido.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
Por favor, que tu amorosa bondad sea para mi consuelo, según tu palabra a tu siervo.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Que tus misericordias vengan a mí, para que pueda vivir; porque tu ley es mi delicia.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Que se decepcionen los soberbios, porque me han derrocado injustamente. Meditaré en tus preceptos.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Que los que te temen se dirijan a mí. Conocerán sus estatutos.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Que mi corazón sea irreprochable ante tus decretos, para que no me decepcione. KAPF
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi alma desfallece por tu salvación. Espero en su palabra.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Mis ojos fallan por tu palabra. Digo: “¿Cuándo me vas a consolar?”
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Porque me he vuelto como un odre en el humo. No olvido sus estatutos.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
¿Cuántos son los días de tu siervo? ¿Cuándo ejecutarás el juicio sobre los que me persiguen?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Los orgullosos han cavado fosas para mí, contrario a su ley.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Todos tus mandamientos son fieles. Me persiguen injustamente. ¡Ayúdenme!
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Casi me habían borrado de la tierra, pero no he abandonado tus preceptos.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Preserva mi vida según tu amorosa bondad, así que obedeceré los estatutos de tu boca. LAMEDH
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
Yahvé, tu palabra está fijada en el cielo para siempre.
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
Tu fidelidad es para todas las generaciones. Tú has establecido la tierra, y ésta permanece.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
Tus leyes permanecen hasta el día de hoy, porque todas las cosas te sirven.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
A menos que tu ley haya sido mi deleite, Habría perecido en mi aflicción.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Nunca olvidaré tus preceptos, porque con ellos me has revivido.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Soy tuyo. Sálvame, porque he buscado tus preceptos.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Los malvados me han esperado para destruirme. Tendré en cuenta sus estatutos.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
He visto un límite a toda perfección, pero tus órdenes son ilimitadas. MEM
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
¡Cómo me gusta tu ley! Es mi meditación todo el día.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Tus mandamientos me hacen más sabio que mis enemigos, porque tus mandamientos están siempre conmigo.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
Tengo más entendimiento que todos mis profesores, porque sus testimonios son mi meditación.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
entiendo más que los ancianos, porque he guardado tus preceptos.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
He guardado mis pies de todo camino malo, para que pueda observar tu palabra.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
No me he apartado de tus ordenanzas, porque tú me has enseñado.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
Qué dulces son tus promesas para mi gusto, ¡más que la miel a mi boca!
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
A través de tus preceptos, obtengo entendimiento; por lo tanto, odio todo camino falso. NUN
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
Tu palabra es una lámpara para mis pies, y una luz para mi camino.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
Lo he jurado y lo he confirmado, que obedeceré tus justas ordenanzas.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Estoy muy afligido. Revísame, Yahvé, según tu palabra.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Acepta, te lo ruego, las ofrendas voluntarias de mi boca. Yahvé, enséñame tus ordenanzas.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Mi alma está continuamente en mi mano, pero no olvidaré su ley.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Los malvados me han tendido una trampa, pero no me he desviado de tus preceptos.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
He tomado sus testimonios como herencia para siempre, porque son la alegría de mi corazón.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
He puesto mi corazón para cumplir tus estatutos para siempre, hasta el final. SAMEKH
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
Odio a los hombres de doble moral, pero me encanta su ley.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Tú eres mi escondite y mi escudo. Espero en su palabra.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Apartaos de mí, malhechores, para guardar los mandamientos de mi Dios.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Sostenme según tu palabra, para que viva. Que no me avergüence de mi esperanza.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Sosténgame, y estaré a salvo, y tendrá respeto por sus estatutos continuamente.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Tú rechazas a todos los que se desvían de tus estatutos, porque su engaño es en vano.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Tú apartas a todos los malvados de la tierra como si fueran escoria. Por eso me encantan sus testimonios.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Mi carne tiembla por temor a ti. Tengo miedo de sus juicios. AYIN
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
He hecho lo que es justo y recto. No me dejes en manos de mis opresores.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Asegura el bienestar de tu sirviente. No dejes que los orgullosos me opriman.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Mis ojos fallan buscando tu salvación, por tu justa palabra.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Trata a tu siervo según tu amorosa bondad. Enséñame tus estatutos.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Soy tu siervo. Dame entendimiento, para que conozca sus testimonios.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Es hora de actuar, Yahvé, ya que infringen tu ley.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
Por eso amo tus mandamientos más que el oro, sí, más que oro puro.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
Por eso considero que todos tus preceptos son correctos. Odio todas las formas falsas. PE
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
Sus testimonios son maravillosos, por eso mi alma los guarda.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
La entrada de tus palabras da luz. Da comprensión a lo simple.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
Abrí la boca de par en par y jadeé, porque anhelaba tus mandamientos.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Vuélvete a mí y ten piedad de mí, como siempre haces con los que aman tu nombre.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Establece mis pasos en tu palabra. No dejes que ninguna iniquidad se enseñoree de mí.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Redímeme de la opresión del hombre, así que observaré tus preceptos.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Haz brillar tu rostro sobre tu siervo. Enséñame tus estatutos.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Arroyos de lágrimas corren por mis ojos, porque no observan su ley. TZADHE
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
Tú eres justo, Yahvé. Sus juicios son rectos.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
Has ordenado tus estatutos con justicia. Son de plena confianza.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Mi celo me agota, porque mis enemigos ignoran tus palabras.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Sus promesas han sido probadas a fondo, y tu siervo los ama.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Soy pequeño y despreciado. No olvido sus preceptos.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
Tu justicia es una justicia eterna. Su ley es la verdad.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
Los problemas y la angustia se han apoderado de mí. Tus mandamientos son mi deleite.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
Tus testimonios son justos para siempre. Dame entendimiento, para que pueda vivir. QOPH
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
He llamado con todo mi corazón. ¡Respóndeme, Yahvé! Mantendré sus estatutos.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
Te he llamado. Sálvame. Obedeceré tus estatutos.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Me levanto antes del amanecer y pido ayuda. Pongo mi esperanza en tus palabras.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mis ojos permanecen abiertos durante las guardias nocturnas, para poder meditar en tu palabra.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Escucha mi voz según tu amorosa bondad. Revísame, Yahvé, según tus ordenanzas.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Se acercan los que siguen la maldad. Están lejos de su ley.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Tú estás cerca, Yahvé. Todos tus mandamientos son la verdad.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
De antaño he conocido por sus testimonios, que los has fundado para siempre. RESH
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
Considera mi aflicción y líbrame, porque no olvido tu ley.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
¡Aboga por mi causa y redímeme! Revívelo según tu promesa.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
La salvación está lejos de los malvados, porque no buscan sus estatutos.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Grandes son tus misericordias, Yahvé. Revísame según tus ordenanzas.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Muchos son mis perseguidores y mis adversarios. No me he desviado de sus testimonios.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Miro a los infieles con repugnancia, porque no observan su palabra.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Considera cómo amo tus preceptos. Revísame, Yahvé, según tu amorosa bondad.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
Todas tus palabras son verdad. Cada una de tus justas ordenanzas perdura para siempre. PECADO Y SHIN
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Los príncipes me han perseguido sin causa, pero mi corazón se queda asombrado con tus palabras.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Me alegro de tu palabra, como quien encuentra un gran botín.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
Odio y aborrezco la falsedad. Me encanta su ley.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Siete veces al día, te alabo, a causa de tus justas ordenanzas.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Los que aman tu ley tienen una gran paz. Nada les hace tropezar.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
He esperado tu salvación, Yahvé. He cumplido tus mandamientos.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Mi alma ha observado tus testimonios. Los quiero mucho.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
He obedecido tus preceptos y tus testimonios, porque todos mis caminos están delante de ti. TAV
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Que mi clamor llegue ante ti, Yahvé. Dame entendimiento según tu palabra.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Que mi súplica llegue ante ti. Líbrame según tu palabra.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Que mis labios pronuncien alabanzas, porque me enseñas tus estatutos.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Que mi lengua cante tu palabra, porque todos tus mandamientos son justicia.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Que tu mano esté lista para ayudarme, porque he elegido tus preceptos.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
He anhelado tu salvación, Yahvé. Su ley es mi deleite.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Deja que mi alma viva, para que te alabe. Deja que tus ordenanzas me ayuden.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Me he extraviado como una oveja perdida. Busca a tu siervo, pues no olvido tus mandamientos.