< Psalms 119 >
1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
ALEF Binecuvântați sunt cei neîntinați pe cale, care umblă în legea DOMNULUI.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Binecuvântați sunt cei ce țin mărturiile lui și îl caută cu întreaga inimă.
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Ei de asemenea nu fac nelegiuire, ei umblă în căile lui.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Tu ne-ai poruncit să ținem stăruitor preceptele tale.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
O, de ar fi fost căile mele rânduite să țină statutele tale!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Atunci nu mă voi rușina când voi respecta toate poruncile tale.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Te voi lăuda cu o inimă dreaptă, după ce voi învăța judecățile tale drepte.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
Voi ține statutele tale, nu mă părăsi de tot. BET
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Cu ce își va curăți un tânăr calea? Ținând seama la ea conform cuvântului tău.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Cu întreaga mea inimă te-am căutat, nu mă lăsa să rătăcesc de la poruncile tale.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
Cuvântul tău l-am ascuns în inima mea, ca să nu păcătuiesc împotriva ta.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Binecuvântat ești tu, DOAMNE, învață-mă statutele tale.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
Cu buzele mele am vestit toate judecățile gurii tale.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
M-am bucurat în calea mărturiilor tale, cât în toate bogățiile.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
Voi medita la preceptele tale și voi lua seama la căile tale.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Mă voi desfăta în statutele tale, nu voi uita cuvântul tău. GIMEL
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Fă mult bine servitorului tău, ca să trăiesc și să țin cuvântul tău.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Deschide-mi ochii să văd lucrurile minunate din legea ta.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Eu sunt străin pe pământ, nu ascunde poruncile tale de mine.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Sufletul meu se frânge de dorința pe care o are pentru judecățile tale tot timpul.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Tu ai mustrat pe cei mândri, care sunt blestemați, care rătăcesc de la poruncile tale.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Îndepărtează de mine ocara și disprețul, fiindcă am păzit mărturiile tale.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Prinți de asemenea au șezut și au vorbit împotriva mea, dar servitorul tău a meditat la statutele tale.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
Mărturiile tale de asemenea sunt desfătarea mea și sfătuitorii mei. DALET
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Sufletul meu se lipește de țărână, dă-mi viață conform cuvântului tău.
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Eu am vestit căile mele și tu m-ai ascultat, învață-mă statutele tale.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Fă-mă să înțeleg calea preceptelor tale, astfel voi vorbi despre minunatele tale lucrări.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Sufletul meu se topește de întristare, întărește-mă conform cuvântului tău.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Îndepărtează de la mine calea minciunii și dă-mi cu har legea ta.
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
Eu am ales calea adevărului, am pus judecățile tale înaintea mea.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
M-am lipit de mărturiile tale, DOAMNE, nu mă da de rușine.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
Voi alerga pe calea poruncilor tale, când îmi vei lărgi inima. HE
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
Învață-mă, DOAMNE, calea statutelor tale și o voi ține până la sfârșit.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Dă-mi înțelegere și voi ține legea ta; da, o voi păzi cu întreaga mea inimă.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Fă-mă să merg pe cărarea poruncilor tale, căci în ea îmi găsesc plăcere.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Apleacă-mi inima la mărturiile tale și nu la poftire.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Abate ochii mei de la a privi deșertăciune; și dă-mi viață pe calea ta.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Întemeiază cuvântul tău servitorului tău, care este devotat temerii de tine.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Abate ocara mea de care mă tem, fiindcă judecățile tale sunt bune.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
Iată, am tânjit după preceptele tale, dă-mi viață în dreptatea ta. VAV
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Lasă de asemenea îndurările tale și salvarea ta să vină la mine, DOAMNE, conform cuvântului tău.
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Astfel voi avea cu ce să răspund celui ce mă ocărăște, căci mă încred în cuvântul tău.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
Și nu lua cuvântul adevărului cu totul din gura mea, pentru că am sperat în judecățile tale.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
Astfel voi ține legea ta continuu pentru totdeauna și întotdeauna.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
Și voi umbla în libertate, căci eu caut preceptele tale.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
Voi vorbi despre mărturiile tale de asemenea în fața împăraților și nu mă voi rușina.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
Și mă voi desfăta în poruncile tale, pe care le-am iubit.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
Mâinile mele de asemenea le voi înălța spre poruncile tale, pe care le-am iubit; și voi medita la statutele tale. ZAYIN
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
Amintește servitorului tău cuvântul, în care m-ai făcut să sper.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
Acesta îmi este mângâierea în necazul meu, căci cuvântul tău mi-a dat viață.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
Cei mândri m-au luat mult în derâdere, totuși nu m-am abătut de la legea ta.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Mi-am amintit de judecățile tale din vechime, DOAMNE, și m-am mângâiat.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
Groaza m-a cuprins din cauza celor stricați care părăsesc legea ta.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Statutele tale au fost cântările mele în casa călătoriei mele.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
Noaptea mi-am amintit de numele tău, DOAMNE, și am ținut legea ta.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
Aceasta am avut, pentru că am ținut preceptele tale. HET
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Tu ești partea mea, DOAMNE, am spus că voi ține cuvintele tale.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Am implorat favoarea ta cu întreaga mea inimă, fii milostiv față de mine conform cuvântului tău.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
M-am gândit la căile mele și mi-am întors picioarele spre mărturiile tale.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
M-am grăbit și nu am întârziat să țin poruncile tale.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Cetele celor stricați m-au jefuit, dar eu nu am uitat legea ta.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
La miezul nopții mă voi scula să îți aduc mulțumiri datorită judecăților tale drepte.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Sunt tovarăș tuturor celor ce se tem de tine și celor ce țin preceptele tale.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
Pământul, DOAMNE, este plin de mila ta, învață-mă statutele tale. TET
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
Tu te-ai purtat bine cu servitorul tău, DOAMNE, conform cuvântului tău.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Învață-mă judecată bună și cunoaștere, căci am crezut poruncile tale.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Înainte să fiu chinuit am rătăcit, dar acum am ținut cuvântul tău.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Tu ești bun și faci bine; învață-mă statutele tale.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
Cei mândri au născocit o minciună împotriva mea, dar voi ține preceptele tale cu întreaga mea inimă.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Inima lor este grasă ca unsoarea; dar eu mă desfăt în legea ta.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Este bine pentru mine că am fost chinuit, ca să învăț statutele tale.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
Legea gurii tale este mai bună pentru mine decât mii de bucăți de aur și argint. IOD
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
Mâinile tale m-au făcut și m-au modelat, dă-mi înțelegere, ca să învăț poruncile tale.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Cei ce se tem de tine se vor veseli când mă vor vedea, deoarece am sperat în cuvântul tău.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Știu, DOAMNE, că judecățile tale sunt drepte și că tu în credincioșie m-ai chinuit.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
Fie, te rog, bunătatea ta milostivă mângâierea mea, conform cuvântului tău față de servitorul tău.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Să vină la mine îndurările tale blânde, ca să trăiesc, fiindcă legea ta este desfătarea mea.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Rușinați fie cei mândri, căci s-au purtat pervers cu mine fără motiv, dar eu voi medita la preceptele tale.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Să se întoarcă la mine cei ce se tem de tine și cei ce au cunoscut mărturiile tale.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Inima mea să fie desăvârșită în statutele tale, ca să nu mă rușinez. CAF
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Sufletul meu se sfârșește după salvarea ta, dar eu sper în cuvântul tău.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Ochii mei se sfârșesc după cuvântul tău, spunând: Când mă vei mângâia?
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Căci am devenit ca un burduf în fum; totuși eu nu uit statutele tale.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
Cât de multe sunt zilele servitorului tău? Când vei face judecată asupra celor ce mă persecută?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Pentru mine au săpat gropi cei mândri, care nu sunt după legea ta.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Toate poruncile tale sunt credincioase, ei mă persecută pe nedrept; ajută-mă.
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Aproape că m-au mistuit de pe pământ; dar eu nu am părăsit preceptele tale.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Dă-mi viață după bunătatea ta iubitoare; astfel voi ține mărturia gurii tale. LAMED
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
Pentru totdeauna, DOAMNE, cuvântul tău este întemeiat în cer.
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
Credincioșia ta este spre toate generațiile, tu ai întemeiat pământul și el dăinuiește.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
Ei dăinuiesc până astăzi conform rânduielilor tale, căci toți sunt servitorii tăi.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Dacă legea ta nu ar fi fost desfătările mele, atunci aș fi pierit în necazul meu.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Nu voi uita niciodată preceptele tale, căci cu ele mi-ai dat viață.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Eu sunt al tău, salvează-mă, fiindcă am căutat preceptele tale.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Cei stricați m-au așteptat pentru a mă nimici, dar eu voi lua aminte la mărturiile tale.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
Am văzut un sfârșit a toată perfecțiunea, dar porunca ta este foarte întinsă. MEM
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
Cât de mult iubesc legea ta! Ea este meditația mea toată ziua.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Prin poruncile tale m-ai făcut mai înțelept decât dușmanii mei, căci ele sunt totdeauna cu mine.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
Am mai multă înțelegere decât toți învățătorii mei, fiindcă mărturiile tale sunt meditația mea.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
Înțeleg mai mult decât bătrânii, pentru că eu țin preceptele tale.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi-am înfrânat picioarele de la fiecare cale rea, ca să țin cuvântul tău.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
Nu m-am depărtat de judecățile tale, pentru că tu m-ai învățat.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
Cât de dulci sunt cuvintele tale pentru cerul gurii mele! Mai dulci decât mierea pentru gura mea!
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
Prin preceptele tale obțin înțelegere, de aceea urăsc toată calea mincinoasă. NUN
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
Cuvântul tău este o lampă pentru picioarele mele și o lumină pentru cărarea mea.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
Am jurat că voi ține judecățile tale drepte și le voi împlini.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Sunt foarte nenorocit; dă-mi viață, DOAMNE, conform cuvântului tău.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Te implor, DOAMNE, primește ofrandele de bunăvoie ale gurii mele și învață-mă judecățile tale.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Sufletul meu este continuu în mâna mea, totuși eu nu uit legea ta.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Cei stricați mi-au întins o capcană, totuși nu m-am rătăcit de la preceptele tale.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
Mărturiile tale le-am luat ca pe o moștenire pentru totdeauna, fiindcă ele sunt bucuria inimii mele.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
Mi-am aplecat inima să împlinesc statutele tale întotdeauna, până la sfârșit. SAMEC
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
Urăsc gândurile deșarte, dar iubesc legea ta.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Tu ești ascunzișul meu și scutul meu, eu sper în cuvântul tău.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Plecați de la mine, voi făcători de rău, căci voi ține poruncile Dumnezeului meu.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Susține-mă conform cuvântului tău, ca să trăiesc; și nu mă lăsa să fiu făcut de rușine datorită speranței mele.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Susține-mă și voi fi în siguranță și voi respecta statutele tale continuu.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Tu ai călcat în picioare pe toți cei ce rătăcesc de la statutele tale, pentru că înșelătoria lor este falsitate.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Tu pui deoparte precum zgura pe toți cei stricați ai pământului, de aceea eu iubesc mărturiile tale.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Carnea mea tremură de teama de tine; și mă tem de judecățile tale. AYIN
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
Eu am făcut judecată și justiție; nu mă lăsa la voia opresorilor mei.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Fii garant pentru servitorul tău pentru bine, nu lăsa pe cei mândri să mă oprime.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Ochii mei se sfârșesc după salvarea ta și după cuvântul dreptății tale.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Poartă-te cu servitorul tău conform milei tale și învață-mă statutele tale.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Eu sunt servitorul tău; dă-mi înțelegere, ca să cunosc mărturiile tale.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Este timpul să lucrezi, DOAMNE, pentru că ei au făcut legea ta fără efect.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
De aceea iubesc poruncile tale mai mult decât aurul; da, mai mult decât aurul pur.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
De aceea socotesc toate preceptele tale ca fiind drepte; și urăsc toată calea mincinoasă. PE
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
Mărturiile tale sunt minunate, de aceea sufletul meu le ține.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
Intrarea cuvintelor tale dă lumină; ea dă înțelegere celui simplu.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
Mi-am deschis gura și am sorbit, căci am tânjit după poruncile tale.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Uită-te la mine și fii milostiv cu mine, așa cum ai obișnuit să faci celor ce iubesc numele tău.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Rânduiește-mi pașii în cuvântul tău și nicio nelegiuire să nu domnească asupra mea.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Eliberează-mă de oprimarea omului, astfel voi ține preceptele tale.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Fă să strălucească fața ta peste servitorul tău; și învață-mă statutele tale.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Râuri de ape curg din ochii mei, pentru că ei nu țin legea ta. ȚADI
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
Drept ești tu, DOAMNE, și integre sunt judecățile tale.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
Mărturiile tale, pe care le-ai poruncit, sunt drepte și foarte credincioase.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Zelul meu m-a mistuit, pentru că dușmanii mei au uitat cuvintele tale.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Cuvântul tău este foarte pur, de aceea servitorul tău îl iubește.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Eu sunt mic și disprețuit, totuși nu uit preceptele tale.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
Dreptatea ta este o dreptate veșnică și legea ta este adevărul.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
Tulburare și chin m-au cuprins, totuși poruncile tale sunt desfătările mele.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
Dreptatea mărturiilor tale este veșnică, dă-mi înțelegere și voi trăi. KOF
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Am strigat cu întreaga mea inimă; ascultă-mă, DOAMNE, eu voi ține statutele tale.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
Am strigat către tine; salvează-mă și voi ține mărturiile tale.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Am întâmpinat răsăritul dimineții și am strigat, am sperat în cuvântul tău.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Ochii mei întâmpină gărzile nopții, ca să meditez la cuvântul tău.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Ascultă-mi vocea conform bunătății tale iubitoare, DOAMNE, dă-mi viață conform judecății tale.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Se apropie cei ce urmăresc ticăloșie, ei sunt departe de legea ta.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Tu ești aproape, DOAMNE; și toate poruncile tale sunt adevăr.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
Referitor la mărturiile tale, am știut din vechime că tu le-ai fondat pentru totdeauna. REȘ
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
Ia aminte la necazul meu și eliberează-mă, căci nu uit legea ta.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Pledează în cauza mea și eliberează-mă, dă-mi viață conform cuvântului tău.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
Salvarea este departe de cei stricați, căci ei nu caută statutele tale.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Mari sunt îndurările tale blânde, DOAMNE, dă-mi viață conform judecăților tale.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Mulți sunt persecutorii mei și dușmanii mei; totuși nu mă abat de la mărturiile tale.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Am privit pe călcătorii de lege și m-am mâhnit, pentru că nu au ținut cuvântul tău.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Vezi cât iubesc preceptele tale, dă-mi viață, DOAMNE, conform bunătății tale iubitoare.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
Cuvântul tău este adevărat de la început și fiecare din judecățile tale drepte dăinuiește pentru totdeauna. ȘIN
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Prinți m-au persecutat fără motiv, dar inima mea se cutremură la cuvântul tău.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Mă bucur la cuvântul tău, ca unul ce găsește mare pradă.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
Urăsc și detest minciuna, dar iubesc legea ta.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
De șapte ori pe zi te laud datorită judecăților tale drepte.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Multă pace au cei ce iubesc legea ta și nimic nu îi va poticni.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
DOAMNE, eu am sperat în salvarea ta și am împlinit poruncile tale.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Sufletul meu a ținut mărturiile tale și le iubesc peste măsură.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
Am ținut preceptele tale și mărturiile tale, căci toate căile mele sunt înaintea ta. TAV
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Să se apropie strigătul meu înaintea ta, DOAMNE, dă-mi înțelegere conform cuvântului tău.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Să ajungă cererea mea înaintea ta, eliberează-mă conform cuvântului tău.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Buzele mele vor rosti laudă, când mă vei învăța statutele tale.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Limba mea va vorbi despre cuvântul tău, pentru că toate poruncile tale sunt dreptate.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Mâna ta să mă ajute, pentru că am ales preceptele tale.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
Am tânjit după salvarea ta, DOAMNE, și legea ta este desfătarea mea.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Lasă sufletul meu să trăiască și te va lăuda; și lasă judecățile tale să mă ajute.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Am rătăcit ca o oaie pierdută; caută pe servitorul tău, pentru că nu uit poruncile tale.