< Psalms 119 >

1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
Boldogok, a kiknek útjok feddhetetlen, a kik az Úr törvényében járnak.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Boldogok, a kik megőrzik az ő bizonyságait, és teljes szívből keresik őt.
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
És nem cselekesznek hamisságot; az ő útaiban járnak.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Te parancsoltad Uram, hogy határozataidat jól megőrizzük.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
Vajha igazgattatnának az én útaim a te rendeléseid megőrzésére!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Akkor nem szégyenülnék meg, ha figyelnék minden parancsolatodra!
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Hálát adok néked tiszta szívből, hogy megtanítottál engem a te igazságod ítéleteire.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
A te rendeléseidet megőrzöm; soha ne hagyj el engem!
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mi módon őrizheti meg tisztán az ifjú az ő útát, ha nem a te beszédednek megtartása által?
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Teljes szívből kerestelek téged: ne engedj eltévedeznem a te parancsolataidtól!
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
Szívembe rejtettem a te beszédedet, hogy ne vétkezzem ellened.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Áldott vagy te, Uram! Taníts meg engem a te rendeléseidre.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
Ajkaimmal hirdetem a te szádnak minden ítéletét.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
Inkább gyönyörködöm a te bizonyságaidnak útjában, mint minden gazdagságban.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
A te határozataidról gondolkodom, és a te ösvényeidre nézek.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Gyönyörködöm a te rendeléseidben; a te beszédedről nem feledkezem el.
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Tégy jól a te szolgáddal, hogy éljek és megtartsam a te beszédedet.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Nyisd meg az én szemeimet, hogy szemléljem a te törvényednek csodálatos voltát.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Jövevény vagyok e földön, ne rejtsd el tőlem a te parancsolataidat.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Elfogyatkozik az én lelkem, a te ítéleteid után való szüntelen vágyódás miatt.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Megdorgálod a kevélyeket; átkozottak, a kik elhajolnak parancsolataidtól.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Fordítsd el rólam a szidalmat és gyalázatot, mert megőriztem a te bizonyságaidat!
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Még ha fejedelmek összeülnek, ellenem beszélnek is; a te szolgád a te rendeléseidről gondolkodik.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
A te bizonyságaid én gyönyörűségem, és én tanácsadóim.
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Lelkem a porhoz tapad; eleveníts meg engem a te igéreted szerint.
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Útaimat elbeszéltem előtted és te meghallgattál engem; taníts meg a te rendeléseidre!
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Add értenem a te határozataidnak útát, hogy gondolkodjam a te csodálatos dolgaidról!
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Sír a lelkem a keserűség miatt; vigasztalj meg a te igéd szerint!
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
A hamisságnak útját távoztasd el tőlem, és a te törvényeddel ajándékozz meg engem!
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
Az igazság útját választottam; a te ítéleteid forognak előttem.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Ragaszkodom a te bizonyságaidhoz; Uram, ne hagyj megszégyenülni!
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
A te parancsolataidnak útján járok, ha megvigasztalod az én szívemet!
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
Taníts meg Uram a te rendeléseidnek útjára, hogy megőrizzem azt mindvégig.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Oktass, hogy megőrizzem a te törvényedet, és megtartsam azt teljes szívemből.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Vezérelj a te parancsolataidnak útján, mert gyönyörködöm abban.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Hajtsd szívemet a te bizonyságaidhoz, és ne a telhetetlenségre.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Fordítsd el az én szemeimet, hogy ne lássanak hiábavalóságot; a te útadon éltess engemet.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Teljesítsd igéretedet a te szolgádnak, a ki fél téged.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Fordítsd el tőlem a gyalázatot, a mitől félek; hiszen jók a te ítéleteid.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
Ímé, kivánkozom a te határozataid után; éltess engem a te igazságod által.
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
És szálljon reám, Uram, a te kegyelmed, a te szabadításod, a mint megigérted,
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Hogy megfelelhessek az engem gyalázónak, hiszen bizodalmam van a te igédben!
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
És az igazságnak beszédét se vedd el soha az én számtól, mert várom a te ítéleteidet!
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
És megtartom a te törvényedet mindenkor és mindörökké.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
És tágas téren járok, mert a te határozataidat keresem.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
És a királyok előtt szólok a te bizonyságaidról, és nem szégyenülök meg.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
És gyönyörködöm a te parancsolataidban, a melyeket szeretek.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
És felemelem kezeimet a te parancsolataidra, a melyeket szeretek, és gondolkodom a te rendeléseidről.
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
Emlékezzél meg a te szolgádnak adott igédről, a melyhez nékem reménységet adtál!
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
Ez vigasztalásom nyomorúságomban, mert a te beszéded megelevenít engem.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
A kevélyek szerfelett gúnyoltak engem; nem hajlottam el a te törvényedtől.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Megemlékezem a te öröktől fogva való ítéleteidről Uram, és vigasztalódom.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
Harag vett rajtam erőt az istentelenek miatt, a kik elhagyták a te törvényedet.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Ének volt rám nézve minden parancsolatod bujdosásomnak hajlékában.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
Uram! a te nevedről emlékezem éjjel, és megtartom a te törvényedet.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
Ez jutott nékem, hogy a te határozataidat megőriztem.
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Azt mondám Uram, hogy az én részem a te beszédeidnek megtartása.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Teljes szívből könyörgök a te színed előtt: könyörülj rajtam a te igéreted szerint!
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
Meggondoltam az én útaimat, és lábaimat a te bizonyságaidhoz fordítom.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Sietek és nem mulasztom el, hogy megtartsam a te parancsolataidat.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Az istentelenek kötelei körülkerítettek engem; de a te törvényedről el nem feledkezem.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
Éjfélkor felkelek, hogy hálát adjak néked, igazságod ítéleteiért.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Társok vagyok mindazoknak, a kik félnek téged, és a kik határozataidat megtartják.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
A te kegyelmeddel, oh Uram, teljes e föld: taníts meg engem rendeléseidre!
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
Jót cselekedtél a te szolgáddal, Uram, a te igéd szerint.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Az okosságnak és tudománynak drága voltára taníts meg engem, mert hiszek a te parancsolataidnak.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Minekelőtte megaláztattam, tévelyegtem vala; most pedig vigyázok a te szódra.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Jó vagy te és jóltevő, taníts meg engem a te rendeléseidre.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
A kevélyek hazugságot költöttek reám, de én teljes szívből megtartom a te parancsolataidat.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Kövér az ő szívök, mint a háj; de én a te törvényedben gyönyörködöm.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Jó nékem, hogy megaláztál, azért, hogy megtanuljam a te rendeléseidet.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
A te szádnak törvénye jobb nékem, mint sok ezer arany és ezüst.
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
A te kezeid teremtettek és erősítettek meg engem; oktass, hogy megtanuljam parancsolataidat.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
A kik téged félnek, látnak engem és örvendeznek, mivel a te igédben van az én reménységem.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Tudom Uram, hogy a te ítéleteid igazak, és igazságosan aláztál meg engem.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
Legyen velem a te kegyelmed, hogy megvígasztalódjam a te szolgádnak tett igéreted szerint.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Szálljon reám a te irgalmasságod, hogy éljek, mert a te törvényedben gyönyörködöm.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Szégyenüljenek meg a kevélyek, a kik csalárdul elnyomtak engem, holott én a te határozataidról gondolkodom.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Forduljanak hozzám, a kik téged félnek, és ismerik a te bizonyságaidat!
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Legyen az én szívem feddhetetlen a te rendeléseidben, hogy meg ne szégyenüljek.
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Elfogyatkozik az én lelkem a te szabadításod kivánása miatt; a te igédben van az én reménységem.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
A te beszéded kivánása miatt elfogyatkoznak az én szemeim, mondván: mikor vígasztalsz meg engem?
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Noha olyanná lettem, mint a füstön levő tömlő; a te rendeléseidről el nem feledkezem.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
Mennyi a te szolgádnak napja, és mikor tartasz ítéletet az én üldözőim felett?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Vermet ástak nékem a kevélyek, a kik nem a te törvényed szerint élnek.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Minden parancsolatod igaz; csalárdul üldöznek engem; segíts meg engem!
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Csaknem semmivé tettek engem e földön, de én nem hagytam el a te határozataidat.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
A te kegyelmed szerint eleveníts meg engem, hogy megőrizhessem a te szádnak bizonyságait.
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
Uram! örökké megmarad a te igéd a mennyben.
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
Nemzedékről nemzedékre van a te igazságod, te erősítetted meg a földet és áll az.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
A te ítéleteid szerint áll minden ma is; mert minden, a mi van, te néked szolgál.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Ha nem a te törvényed lett volna az én gyönyörűségem, akkor elvesztem volna az én nyomorúságomban.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Soha sem feledkezem el a te határozataidról, mert azok által elevenítettél meg engem.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Tied vagyok, tarts meg engem, mert a te határozataidat keresem.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Vártak rám a gonoszok, hogy elveszessenek, de én a te bizonyságaidra figyelek.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
Látom, minden tökéletes dolognak vége van, de a te parancsolatodnak nincs határa.
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
Mely igen szeretem a te törvényedet, egész napestig arról gondolkodom!
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Az én ellenségeimnél bölcsebbé teszel engem a te parancsolataiddal, mert mindenkor velem vannak azok.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
Minden tanítómnál értelmesebb lettem, mert a te bizonyságaid az én gondolataim.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
Előrelátóbb vagyok, mint az öreg emberek, mert vigyázok a te határozataidra.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
Minden gonosz ösvénytől visszatartóztattam lábaimat, hogy megtartsam a te beszédedet.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
Nem távoztam el a te ítéleteidtől, mert te oktattál engem.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
Mily édes az én ínyemnek a te beszéded; méznél édesbb az az én számnak!
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
A te határozataidból leszek értelmes, gyűlölöm azért a hamisságnak minden ösvényét.
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
Az én lábamnak szövétneke a te igéd, és ösvényemnek világossága.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
Megesküdtem és megállom, hogy megtartom a te igazságodnak ítéleteit.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Felette nagy nyomorúságban vagyok; Uram, eleveníts meg a te igéd szerint.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Szájamnak önkéntes áldozatai legyenek kedvesek előtted Uram! és taníts meg a te ítéleteidre.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Lelkem mindig veszedelemben van, mindazáltal a te törvényedről el nem feledkezem.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Tőrt vetettek ellenem az istentelenek, de a te határozataidtól el nem tévelyedtem.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
A te bizonyságaid az én örökségem mindenha, mert szívemnek örömei azok.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
Az én szívem hajlik a te rendeléseid teljesítésére mindenha és mindvégig.
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
Az állhatatlanokat gyűlölöm, de a te törvényedet szeretem.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Menedékem és paizsom vagy te; igédben van az én reménységem.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Távozzatok tőlem gonoszok, hogy megőrizzem az én Istenemnek parancsolatait.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Támogass engem a te beszéded szerint, hogy éljek, és ne engedd, hogy megszégyenüljek reménységemben.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Segélj, hogy megmaradjak, és gyönyörködjem a te rendeléseidben szüntelen.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Megtapodod mindazokat, a kik rendeléseidtől elhajolnak, mert az ő álnokságuk hazugság.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Mint salakot mind elveted e földnek istenteleneit, azért szeretem a te bizonyságaidat.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Borzad testem a tőled való félelem miatt, és félek a te ítéleteidtől.
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
Méltányosságot és igazságot cselekedtem; ne adj át nyomorgatóimnak!
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Légy kezes a te szolgádért az ő javára, hogy a kevélyek el ne nyomjanak engem.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Szemeim epekednek a te szabadításod és a te igazságod beszéde után.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Cselekedjél a te szolgáddal a te kegyelmességed szerint, és a te rendeléseidre taníts meg engem!
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Szolgád vagyok, oktass, hogy megismerjem a te bizonyságaidat!
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Ideje, hogy az Úr cselekedjék; megrontották a te törvényedet.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
Inkább szeretem azért a te parancsolataidat, mint az aranyat, mint a legtisztább aranyat.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
Igaznak tartom azért minden határozatodat, és a hamisságnak minden ösvényét gyűlölöm.
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
Csodálatosak a te bizonyságaid, azért az én lelkem megőrzi azokat.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
A te beszéded megnyilatkozása világosságot ad, és oktatja az együgyűeket.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
Szájamat feltátom és lihegek, mert kivánom a te parancsolataidat.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Tekints reám és könyörülj rajtam, a miképen szoktál a te nevednek kedvelőin.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Vezéreld útamat a te igéd szerint, és ne engedd, hogy valami hamisság uralkodjék rajtam!
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Oltalmazz meg az emberek erőszakosságától, hogy megőrizzem a te határozataidat!
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
A te orczádat világosítsd meg a te szolgádon, és taníts meg a te rendeléseidre!
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Víznek folyásai erednek az én szemeimből azok miatt, a kik nem tartják meg a te törvényedet.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
Igaz vagy Uram, és a te ítéleted igazságos.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
A te bizonyságaidat igazságban és hűségben jelentetted meg, és mindenek felett való egyenességben.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Buzgóságom megemészt engem, mert elfeledkeztek a te beszédedről az én ellenségeim.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Felettébb tiszta a te beszéded, és a te szolgád szereti azt.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Kicsiny vagyok én és megvetett, de a te határozataidról el nem feledkezem.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
A te igazságod igazság örökké, és a te törvényed igaz.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
Nyomorúság és keserűség ért engem, de a te parancsolataid gyönyörűségeim nékem.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
A te bizonyságaidnak igazsága örökkévaló; oktass, hogy éljek!
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Teljes szívből kiáltok hozzád, hallgass meg, Uram! megtartom a te rendeléseidet.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
Segítségül hívlak: tarts meg engem, és megőrzöm a te bizonyságaidat.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Hajnal előtt felkelek, kiáltok hozzád; a te beszédedben van reménységem.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Szemeim megelőzik az éjjeli őrséget, hogy a te beszédedről gondolkodjam.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Hallgasd meg az én szómat a te kegyelmességed szerint, Uram! Eleveníts meg a te jóvoltod szerint!
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Közelgetnek hozzám az én gonosz háborgatóim, a kik a te törvényedtől messze távoztak.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Közel vagy te, Uram! és minden te parancsolatod igazság.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
Régtől fogva tudom a te bizonyságaid felől, hogy azokat örökké állandókká tetted.
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
Lásd meg az én nyomorúságomat és szabadíts meg engem; mert a te törvényedről nem felejtkezem el!
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Te perelj peremben és ments meg; a te beszéded szerint eleveníts meg engem!
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
Távol van a gonoszoktól a szabadítás, mert nem törődnek a te rendeléseiddel.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Nagy a te irgalmasságod, Uram! A te ítéletid szerint eleveníts meg engem.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Sokan vannak az én háborgatóim és üldözőim, de nem térek el a te bizonyságaidtól.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Láttam a hűteleneket és megundorodtam, hogy a te mondásodat meg nem tartják.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Lásd meg Uram, hogy a te határozataidat szeretem; a te kegyelmességed szerint eleveníts meg engem!
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
A te igédnek summája igazság, és a te igazságod ítélete mind örökkévaló.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
A fejedelmek ok nélkül üldöztek engem; de a te igédtől félt az én szívem.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Gyönyörködöm a te beszédedben, mint a ki nagy nyereséget talált.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
A hamisságot gyűlölöm és útálom; a te törvényedet szeretem.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Naponként hétszer dicsérlek téged, a te igazságodnak ítéleteiért.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
A te törvényed kedvelőinek nagy békességök van, és nincs bántódásuk.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
Várom a te szabadításodat, oh Uram! és a te parancsolataidat cselekszem.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Az én lelkem megtartja a te bizonyságaidat, és azokat igen szeretem.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
Megtartom a te határozataidat és bizonyságaidat, mert minden útam nyilván van előtted.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Oh Uram! hadd szálljon az én könyörgésem a te színed elé; tégy bölcscsé engem a te igéd szerint.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Jusson elődbe az én imádságom; a te beszéded szerint szabadíts meg engem!
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Ajkaim dicséretet zengjenek, mert megtanítasz a te rendeléseidre.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Nyelvem a te beszédedről énekel, mert minden parancsolatod igaz.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Legyen segítségemre a te kezed, mert a te határozataidat választottam!
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
Uram! vágyódom a te szabadításod után, és a te törvényed nékem gyönyörűségem.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Éljen az én lelkem, hogy dicsérjen téged, és a te ítéleteid segítsenek rajtam!
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Tévelygek, mint valami elveszett juh: keresd meg a te szolgádat; mert a te parancsolataidat nem felejtettem el!

< Psalms 119 >