< Psalms 119 >
1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
Alléluiah! Heureux ceux qui, dans leur voie, conservent l'innocence, et cheminent en la loi du Seigneur.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Heureux ceux qui méditent ses témoignages, et qui le cherchent de toute leur âme.
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Car les ouvriers d'iniquité n'ont point marché dans ses voies.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Tu as intimé tes commandements, pour qu'ils soient scrupuleusement gardés.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
Puissent mes voies être dirigées vers l'accomplissement de tes ordonnances!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Alors je ne serai point confondu, puisque j'aurai eu mes yeux sur tous tes commandements.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Je te rendrai gloire en la droiture de mon cœur, de ce que j'aurai appris les jugements de ta justice.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
Je garderai tes ordonnances; ne me délaisse pas sans retour.
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Comment le jeune homme maintiendra-t-il droite sa voie? En gardant tes paroles.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Je t'ai cherché de toute mon âme; ne me repousse pas de tes commandements.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
J'ai renfermé dans le secret de mon cœur toutes tes paroles pour ne point pécher contre toi.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Tu es béni, Seigneur, enseigne-moi tes préceptes.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
J'ai publié de mes lèvres tous les jugements de ta bouche.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
Je me suis complu dans la voie de tes témoignages, autant que dans la possession de toutes les richesses.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
Je méditerai sur tes commandements, et je considèrerai tes voies.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
J'étudierai tes préceptes, et je n'oublierai point tes paroles.
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Récompense ton serviteur; et je vivrai, et je garderai tes paroles.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Ote le voile de mes yeux, et je comprendrai les merveilles de ta loi.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Je suis passager sur la terre, ne me cache pas tes commandements.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Mon âme a brûlé, en tout temps, du désir de ta loi.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Tu as châtié les superbes; maudits soient ceux qui s'écartent de tes commandements.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Délivre-moi de l'opprobre et du mépris, car j'ai recherché tes témoignages.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Les princes se sont assis, et ils ont mal parlé de moi; mais ton serviteur méditait sur tes ordonnances.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
Et tes témoignages sont mon étude, et tes conseils mon conseil.
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mon âme est attachée à la terre; vivifie-moi selon ta promesse.
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Je t'ai fait connaître mes voies, et tu m'as écouté; enseigne-moi tes préceptes.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Apprends-moi la voie de tes préceptes, et je méditerai sur tes merveilles.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mon âme s'est assoupie dans l'abattement; fortifie-moi de tes paroles.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Éloigne de moi la voie de l'iniquité, et fais-moi miséricorde à cause de ta loi.
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
J'ai choisi la voie de la vérité, et je n'ai point oublié tes jugements.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Je me suis attaché à tes témoignages, Seigneur; ne m'humilie pas.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
J'ai couru dans la voie de tes commandements, lorsque tu as dilaté mon cœur.
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
Fais, Seigneur, que la voie de tes commandements soit ma loi, et je la chercherai toujours.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Donne-moi l'intelligence, et j'approfondirai ta loi, et je la garderai dans le fond de mon âme.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Guide-moi dans le sentier de tes commandements; car c'est celui-là que j'ai désiré.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Incline mon cœur vers tes témoignages, et non vers la convoitise.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Détourne mes yeux, pour qu'ils ne voient point les vanités; vivifie-moi en ta loi.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Confirme ta parole en ton serviteur, pour qu'il craigne de te déplaire.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Ôte-moi l'opprobre du péché que j'ai appréhendé; car tes jugements me sont délectables.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
Voilà que j'ai désiré tes commandements; vivifie-moi en ta justice.
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Seigneur, que ta miséricorde me vienne, et ton salut, comme tu me l'as promis.
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Et je pourrai répondre à ceux qui m'outragent, car j'ai espéré en tes paroles.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
Ne retire point à jamais de ma bouche la parole de vérité, car j'ai surabondamment espéré en tes jugements.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
Et je garderai ta loi toujours, dans tous les siècles des siècles.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
Et je marchais au large, parce que j'avais recherché tes commandements.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
Et devant les rois je parlais de tes témoignages, et je n'avais aucune honte.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
Et je méditais tes commandements, que j'ai toujours tant aimés.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
Et j'ai levé les mains vers tes commandements, que j'aime, et j'ai médité sur tes préceptes.
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
Souviens-toi de tes paroles à ton serviteur; en elles tu m'as donné d'espérer.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
Elles m'ont consolé dans mon abaissement, et ta parole m'a vivifié.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
Les superbes ont agi envers moi avec une extrême injustice; mais je n'ai point dévié de ta loi.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Je me suis souvenu, Seigneur, de tes jugements éternels, et j'ai été consolé.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
Le découragement m'a pris, à la vue des pécheurs qui abandonnaient ta loi.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Mais, dans le lieu de mon pèlerinage, je chantais encore tes préceptes.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
Je me souvenais de ton nom, Seigneur, pendant la nuit, et je gardais ta loi.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
Et cette grâce m'a été faite, parce que j'avais recherché tes préceptes.
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Tu es mon partage, Seigneur; j'ai dit que je garderais ta loi.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
J'ai demandé de toute mon âme à voir ton visage; fais-moi miséricorde selon ta parole.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
J'ai pensé à tes voies, et j'ai tourné mes pas vers tes témoignages.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Je me suis préparé sans trouble à garder tes commandements.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Les liens des pécheurs m'ont enlacé; mais je n'ai point oublié ta loi.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
Au milieu de la nuit, je me levais pour te rendre grâce de tes jugements et de tes ordonnances.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Je suis partisan de tous ceux qui te craignent et qui gardent tes commandements.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
La terre, Seigneur, est pleine de tes miséricordes; enseigne-moi tous tes préceptes.
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
Seigneur, tu as usé de bonté avec ton serviteur, selon ta parole.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Enseigne-moi la bonté, la discipline et la science, parce que j'ai eu foi en tes commandements.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Avant d'être humilié, j'ai failli; aussi ai-je gardé ta parole.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Tu es bon, Seigneur, et en ta bonté enseigne-moi tes ordonnances.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
L'iniquité des superbes s'est multipliée contre moi; pour moi, j'approfondirai tes commandements au fond de mon cœur.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Leur cœur s'est coagulé comme du laitage, et moi j'ai médité ta loi.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Il est heureux pour moi que tu m'aies humilié, pour que j'apprisse tes ordonnances.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
La loi qui sort de ta bouche est meilleure pour moi que des millions d'or et d'argent.
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
Ce sont tes mains qui m'ont formé et pétri; donne-moi l'intelligence, et je m'instruirai de tes commandements.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Ceux qui te craignent me verront, et ils seront réjouis, parce que j'ai surabondamment espéré en tes promesses.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Seigneur, je sais que tes jugements sont la justice même, et que tu m'as humilié selon ta vérité.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
Et maintenant, que ta miséricorde me vienne et me console, comme tu l'as promis à ton serviteur.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Que tes miséricordes me viennent, et je vivrai, parce que ta loi est l'objet de ma méditation.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Qu'ils soient confondus, les superbes, parce qu'ils ont été injustes envers moi; pour moi, je méditerai sur tes commandements.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Que ceux qui te craignent viennent à moi, et ceux qui connaissent tes témoignages.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Qu'en tes préceptes mon cœur soit trouvé sans tache, pour que je ne sois point confondu.
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mon âme s'est épuisée à réclamer ton secours, tant j'avais espéré en tes paroles!
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Mes yeux se sont éteints dans l'attente de ta parole, disant: Quand me consoleras-tu?
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Me voici comme une outre pendant la gelée; et pourtant je n'ai point oublié tes préceptes.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
Combien ton serviteur comptera-t-il encore de jours? Quand jugeras-tu ceux qui me persécutent?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Les méchants m'ont raconté des choses vaines; mais ce n'était point comme ta loi, Seigneur.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Tous tes commandements sont vérité; ils m'ont poursuivi injustement, protège-moi.
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Peu s'en est fallu qu'ils ne m'aient achevé sur la terre; moi cependant je n'ai point délaissé tes commandements.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Vivifie-moi selon ta miséricorde, et je garderai les témoignages de ta bouche.
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
Seigneur, ta parole demeure dans le ciel éternellement;
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
Ta vérité passe de génération en génération; tu as fondé la terre, et elle subsiste.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
Comme tu l'as réglé, le jour continue de paraître; car tout t'obéit.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Si ta loi n'était point ma continuelle étude, je périrais dans l'humiliation.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Je n'oublierai jamais tes ordonnances, car en elles tu m'as vivifié.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Je suis à toi, sauve-moi; car j'ai recherché tes préceptes.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Les pécheurs m'ont épié pour me perdre; mais j'avais compris tes témoignages.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
J'ai vu la fin de toute œuvre, même la plus parfaite; seule ta loi est éternelle.
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
Que j'aime ta loi, Seigneur! elle est tout le jour l'objet de ma méditation.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Plus qu'à mes ennemis tu m'as fait goûter ta loi, car elle est toujours devant moi.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
J'ai eu plus d'intelligence que ceux qui m'ont instruit, car tes témoignages sont ma méditation.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
J'ai eu plus d'intelligence que les anciens, car j'ai cherché tes commandements.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
J'ai détourné mes pieds de toute voie mauvaise, afin de garder tes paroles.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
Je n'ai point dévié de tes jugements, parce que tu as été mon législateur.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
Que tes paroles sont douces à mon palais! elles le sont plus que le miel à ma bouche.
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
Je tiens mon intelligence de tes préceptes; aussi ai-je en haine toute voie d'iniquité.
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
Ta loi est la lampe de mes pieds et la lumière de mes sentiers.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
J'ai juré et résolu de garder les jugements de ta justice.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
J'ai été profondément humilié, Seigneur; vivifie-moi selon ta parole.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Seigneur, aie pour agréables les offrandes volontaires de ma bouche, et enseigne-moi tes jugements.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Mon âme est toujours en tes mains, et je n'ai point oublié ta loi.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Les pécheurs m'ont tendu des pièges, et je n'ai point dévié de tes commandements.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
J'ai eu pour héritage éternel tes témoignages, et ils sont le tressaillement de mon cœur.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
J'ai incliné mon cœur à toujours agir selon tes ordonnances, en vue de ma rétribution.
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
Je hais les méchants, et j'aime ta loi.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Tu es mon champion et mon appui; j'ai surabondamment espéré en tes promesses.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Éloignez-vous de moi, pervers, et j'approfondirai les commandements de mon Dieu.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Soutiens-moi, Seigneur, selon ta parole, et vivifie-moi; et que je ne sois point confondu en mon attente.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Secours-moi, et je serai sauvé, et je méditerai toujours sur tes préceptes.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Tu as réduit à néant tous ceux qui se sont éloignés de tes jugements, parce que leur pensée est inique.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
J'ai compté comme pécheurs tous les prévaricateurs de la terre; c'est pourquoi j'aime tes témoignages.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Transperce mes chairs de ta crainte, car j'ai toujours redouté tes jugements.
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
J'ai été droit dans mes jugements et ma justice; ne me livre pas à ceux qui me nuisent.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Affermis ton serviteur dans le bien; que les superbes ne le calomnient pas.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Mes yeux ont défailli à force d'attendre mon salut et la parole de ton équité.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Traite ton serviteur selon ta miséricorde, et enseigne-moi tes préceptes.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Je suis ton serviteur; donne-moi l'intelligence, et je connaîtrai tes témoignages.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Le temps d'agir est venu pour le Seigneur; car ils ont renversé ta loi.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
C'est pour cela que j'ai aimé tes commandements plus que l'or et la topaze.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
Aussi me suis-je dirigé selon tes commandements; j'ai pris en haine la voie de l'iniquité.
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
Tes témoignages sont merveilleux; aussi mon âme les a recherchés.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
La manifestation de tes paroles éclairera et instruira les plus jeunes enfants.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
J'ai ouvert la bouche, et je suis resté haletant du désir de tes commandements.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Regarde-moi, et faites-moi miséricorde, comme il est juste envers ceux qui aiment ton nom.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Dirige mes pas selon ta parole, et que nulle iniquité ne soit maîtresse de moi.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Délivre-moi des fausses accusations des hommes, et je garderai tes commandements.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Fais que brille ton visage sur ton serviteur, et enseigne-moi tes préceptes.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Mes yeux se sont fondus en des torrents de larmes, parce que je n'avais point gardé ta loi.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
Tu es juste, Seigneur, et tes jugements sont droits.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
Tu nous as recommandé tes témoignages, comme étant la justice et la vérité.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Ton zèle m'a consumé, parce que mes ennemis avaient oublié tes paroles.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Ta parole est éprouvée comme un feu ardent, et ton serviteur l'aime.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Et, quoique jeune et méprisé, je n'ai point oublié tes préceptes.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
Ta justice est la justice éternelle, et ta loi, la vérité.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
La tribulation et la détresse sont venues me trouver; tes commandements ont été ma méditation.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
Tes témoignages sont une justice éternelle; donne-m'en l'intelligence, et je vivrai.
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
J'ai crié au fond de mon âme; exauce-moi, Seigneur, et je rechercherai tes préceptes.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
J'ai crié vers toi; sauve-moi, et je garderai tes témoignages.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Je me suis levé avant le jour, et j'ai crié, tant j'espérais en tes promesses.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mes yeux se sont ouverts avant l'aurore, pour méditer tes paroles.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Écoute ma voix. Seigneur, selon ta miséricorde; vivifie-moi selon ton jugement.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Mes persécuteurs se sont approchés de l'iniquité, et ils se sont éloignés de ta loi.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Tu es proche, Seigneur, et toutes tes voies sont vérité.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
J'ai reconnu dès le commencement, par tes témoignages, que tu les avais fondés pour tous les siècles.
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
Vois mon humiliation, et délivre-moi; car je n'ai point oublié ta loi.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Juge ma cause, et rachète-moi; vivifie-moi selon ta parole.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
Le salut est loin des pécheurs, parce qu'ils n'ont point, recherché tes préceptes.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Tes miséricordes sont abondantes, Seigneur; vivifie-moi selon ton jugement.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Ceux qui me persécutent et m'oppriment sont nombreux; cependant je ne me suis point écarté de tes témoignages.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
J'ai vu les insensés, et je me suis consumé, parce qu'ils n'avaient point gardé tes paroles.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Vois, Seigneur, combien j'aime ta loi! vivifie-moi selon ta miséricorde.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
La vérité est le principe de tes paroles, et tous les jugements de ta justice sont éternels.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Les princes m'ont persécuté sans cause; mais mon cœur n'a redouté que tes paroles.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Je me réjouirai de tes paroles, comme celui qui trouve un riche butin.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
Je hais l'iniquité, je l'ai en abomination; j'aime ta loi.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Sept fois le jour je t'ai loué, à cause des jugements de ta justice.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Ceux qui aiment ta loi jouissent d'une paix profonde, et il n'est point pour eux de scandale.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
J'ai attendu ton salut, Seigneur, et j'ai aimé tes commandements.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Mon âme a gardé tes témoignages; elle les a vivement aimés.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
J'ai gardé tes commandements et tes témoignages, parce que toutes mes voies sont en ta présence. Seigneur.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Que ma prière. Seigneur, arrive jusqu'à toi; donne-moi l'intelligence selon ta parole.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Que ma demande. Seigneur, arrive jusqu'à toi; délivre-moi selon ta parole.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Que mes lèvres chantent un hymne, quand tu m'auras enseigné tes préceptes.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Que ma langue publie tes promesses, parce que tous tes commandements sont la justice.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Que ta main se prête à me sauver, parce que j'ai choisi ta loi.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
J'ai désiré ton salut. Seigneur, et ta loi est l'objet de ma méditation.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Mon âme vivra et te louera, et tes jugements seront mon soutien.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
J'ai été errant comme une brebis égarée; cherche ton serviteur, parce que je n'ai point oublié ta loi.