< Psalms 119 >

1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
ALEPH Heureux ceux dont les voies sont irréprochables, qui marchent selon la loi de Yahvé.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Heureux ceux qui gardent ses statuts, qui le cherchent de tout leur cœur.
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
Oui, ils ne font rien de mal. Ils marchent dans ses voies.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Tu as ordonné tes préceptes, que nous devons leur obéir pleinement.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
Oh, si mes voies étaient fermes pour obéir à tes statuts!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Alors je ne serais pas déçu, quand je considère tous tes commandements.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Je te louerai avec droiture de cœur, quand j'apprends tes jugements justes.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
J'observerai tes statuts. Ne m'abandonne pas complètement.
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
BETH Comment un jeune homme peut-il garder sa voie pure? En vivant selon ta parole.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Je t'ai cherché de tout mon cœur. Ne me laisse pas m'éloigner de tes commandements.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
J'ai caché ta parole dans mon cœur, pour ne pas pécher contre toi.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Béni sois-tu, Yahvé. Apprends-moi tes statuts.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
Avec mes lèvres, J'ai déclaré toutes les ordonnances de ta bouche.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
Je me suis réjoui sur le chemin de tes témoignages, autant que dans toutes les richesses.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
Je méditerai sur tes préceptes, et réfléchissez à votre façon de faire.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Je ferai mes délices de tes statuts. Je n'oublierai pas ta parole.
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
GIMEL Fais du bien à ton serviteur. Je vivrai et j'obéirai à ta parole.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Ouvrez mes yeux, pour que je voie les merveilles de ta loi.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Je suis un étranger sur la terre. Ne me cachez pas vos commandements.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Mon âme se consume de désir pour tes ordonnances en tout temps.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Tu as réprimandé les orgueilleux qui sont maudits, qui s'éloignent de tes commandements.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Éloigne de moi l'opprobre et le mépris, car j'ai observé tes lois.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Quand les princes s'asseyent et me calomnient, ton serviteur méditera sur tes statuts.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
Tes statuts sont mes délices, et mes conseillers.
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
DALETH Mon âme est couchée dans la poussière. Ranime-moi selon ta parole!
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
J'ai exposé mes voies, et tu m'as répondu. Apprends-moi tes statuts.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Fais-moi comprendre l'enseignement de tes préceptes! Alors je méditerai sur tes merveilles.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mon âme est fatiguée par la tristesse; fortifie-moi selon ta parole.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Garde-moi de la voie de la tromperie. Accorde-moi ta loi gracieusement!
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
J'ai choisi la voie de la vérité. J'ai mis vos ordonnances devant moi.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Je m'attache à tes statuts, Yahvé. Ne me laissez pas être déçu.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
Je cours dans le sentier de tes commandements, car tu as libéré mon cœur.
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
HE Enseigne-moi, Yahvé, la voie de tes statuts. Je les garderai jusqu'à la fin.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Donne-moi l'intelligence, et je garderai ta loi. Oui, j'y obéirai de tout mon cœur.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Dirige-moi dans le chemin de tes commandements, car je me réjouis d'eux.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Tourne mon cœur vers tes statuts, et non vers un gain égoïste.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Détourne mes yeux des choses sans valeur. Ravivez-moi dans vos voies.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Accomplis ta promesse à ton serviteur, pour que vous soyez craint.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Otez le déshonneur que je redoute, car tes ordonnances sont bonnes.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
Voici, j'ai envie de tes préceptes! Ravivez-moi dans votre justice.
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
VAV Que ta bonté vienne aussi à moi, Yahvé, ton salut, selon ta parole.
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
Ainsi, je répondrai à celui qui me fait des reproches, car j'ai confiance en ta parole.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
N'arrache pas de ma bouche la parole de vérité, car j'ai mis mon espoir dans vos ordonnances.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
Ainsi, j'obéirai sans cesse à ta loi, pour toujours et à jamais.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
Je marcherai dans la liberté, car j'ai cherché tes préceptes.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
Je parlerai aussi de tes statuts devant les rois, et vous ne serez pas déçu.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
Je ferai mes délices de tes commandements, parce que je les aime.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
Je tends les mains vers tes commandements, que j'aime. Je méditerai sur tes statuts.
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
ZAYIN Souviens-toi de ta parole envers ton serviteur, parce que tu m'as donné de l'espoir.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
C'est ma consolation dans ma détresse, car ta parole m'a fait revivre.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
Les arrogants se moquent excessivement de moi, mais je ne m'écarte pas de ta loi.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Je me souviens de tes ordonnances d'autrefois, Yahvé, et je me suis consolé.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
L'indignation s'est emparée de moi, à cause des méchants qui abandonnent ta loi.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Tes statuts ont été mes chants dans la maison où je vis.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
Je me suis souvenu de ton nom, Yahvé, dans la nuit, et j'obéis à ta loi.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
C'est mon chemin, que je garde tes préceptes.
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
HETH Yahvé est mon partage. J'ai promis d'obéir à vos paroles.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
J'ai cherché ta faveur de tout mon cœur. Sois miséricordieux envers moi selon ta parole.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
J'ai réfléchi à ma façon de faire, et tourné mes pas vers tes statuts.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Je me dépêcherai, et ne tarderai pas, pour obéir à tes commandements.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Les cordes des méchants me lient, mais je n'oublierai pas votre loi.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
A minuit, je me lèverai pour te rendre grâce, à cause de vos justes ordonnances.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Je suis l'ami de tous ceux qui te craignent, de ceux qui observent tes préceptes.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
La terre est pleine de ta bonté, Yahvé. Apprends-moi tes statuts.
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
TETH Tu as bien traité ton serviteur, selon ta parole, Yahvé.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Enseigne-moi le bon jugement et la connaissance, car je crois en tes commandements.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Avant d'être affligé, je me suis égaré; mais maintenant j'observe ta parole.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Tu es bon, et tu fais le bien. Apprends-moi tes statuts.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
Les orgueilleux m'ont entaché de mensonge. De tout mon cœur, je garderai tes préceptes.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Leur cœur est aussi dur que la graisse, mais je me réjouis de ta loi.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Il est bon pour moi que j'aie été affligé, pour que j'apprenne tes statuts.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
La loi de ta bouche vaut mieux pour moi que des milliers de pièces d'or et d'argent.
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
YODH Tes mains m'ont fait et m'ont formé. Donne-moi l'intelligence, afin que j'apprenne tes commandements.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Ceux qui te craignent me verront et se réjouiront, parce que j'ai mis mon espoir dans ta parole.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Yahvé, je sais que tes jugements sont justes, que c'est par fidélité que tu m'as affligé.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
S'il vous plaît, que votre bonté soit pour mon confort, selon ta parole, à ton serviteur.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Que tes tendres compassions viennent à moi, afin que je vive; car ta loi fait mes délices.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Que les orgueilleux soient déçus, car c'est à tort qu'ils m'ont renversé. Je méditerai sur tes préceptes.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Que ceux qui te craignent se tournent vers moi. Ils connaîtront vos statuts.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Que mon cœur soit irréprochable envers tes décrets, pour que je ne sois pas déçu.
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
KAPF Mon âme se languit de ton salut. J'espère en ta parole.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Mes yeux se languissent de ta parole. Je dis: « Quand me consoleras-tu? »
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Car je suis devenu comme une outre à vin dans la fumée. Je n'oublie pas vos statuts.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
Combien de jours compte ton serviteur? Quand exécuteras-tu le jugement sur ceux qui me persécutent?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Les orgueilleux ont creusé des fosses pour moi, contraire à votre loi.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Tous tes commandements sont fidèles. Ils me persécutent à tort. Aidez-moi!
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Ils m'avaient presque effacé de la terre, mais je n'ai pas abandonné tes préceptes.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Préserve ma vie selon ta bonté, alors j'obéirai aux lois de ta bouche.
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
LAMEDH Yahvé, ta parole est fixée dans les cieux pour toujours.
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
Ta fidélité s'étend à toutes les générations. Tu as établi la terre, et elle demeure.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
Tes lois demeurent jusqu'à ce jour, car toutes choses te servent.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Si ta loi n'avait pas fait mes délices, J'aurais péri dans mon affliction.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Je n'oublierai jamais tes préceptes, car avec eux, tu m'as fait revivre.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Je suis à toi. Sauve-moi, car j'ai cherché tes préceptes.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Les méchants m'ont attendu, pour me détruire. Je prendrai en considération vos statuts.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
J'ai vu une limite à toute perfection, mais vos ordres sont illimités.
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
MEM Comme j'aime ta loi! C'est ma méditation toute la journée.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Tes commandements me rendent plus sage que mes ennemis, car tes commandements sont toujours avec moi.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
J'ai plus de compréhension que tous mes professeurs, car vos témoignages sont ma méditation.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
que je comprends mieux que les personnes âgées, parce que j'ai gardé tes préceptes.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
J'ai gardé mes pieds de toute mauvaise voie, pour que je puisse observer ta parole.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
Je ne me suis pas détourné de tes ordonnances, car tu m'as appris.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
Comme tes promesses sont douces à mon goût, plus que du miel dans ma bouche!
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
Par tes préceptes, j'obtiens la compréhension; c'est pourquoi je déteste toute voie fausse.
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
NUN Ta parole est une lampe pour mes pieds, et une lumière pour mon chemin.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
J'ai juré, et je l'ai confirmé, que j'obéirai à tes justes ordonnances.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Je suis très affligé. Ranime-moi, Yahvé, selon ta parole.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Accepte, je t'en prie, les offrandes volontaires de ma bouche. Yahvé, enseigne-moi tes ordonnances.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Mon âme est continuellement dans ma main, mais je n'oublierai pas votre loi.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Les méchants m'ont tendu un piège, mais je ne me suis pas écarté de vos préceptes.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
J'ai pris vos témoignages comme un héritage pour toujours, car ils sont la joie de mon cœur.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
J'ai mis mon cœur à pratiquer tes lois pour toujours, même jusqu'à la fin.
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
SAMEKH Je déteste les hommes à double esprit, mais j'aime votre loi.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Tu es ma cachette et mon bouclier. J'espère en ta parole.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Éloignez-vous de moi, méchants, afin que je puisse garder les commandements de mon Dieu.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Soutiens-moi selon ta parole, afin que je vive. Que je n'aie pas honte de mon espérance.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Tenez-moi, et je serai en sécurité, et respectera sans cesse vos statuts.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Tu rejettes tous ceux qui s'écartent de tes statuts, car leur ruse est vaine.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Tu as fait disparaître tous les méchants de la terre comme des scories. C'est pourquoi j'aime vos témoignages.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Ma chair tremble par peur de toi. J'ai peur de vos jugements.
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
AYIN J'ai fait ce qui est juste et équitable. Ne me laissez pas à mes oppresseurs.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Veillez au bien-être de votre serviteur. Ne laisse pas les orgueilleux m'opprimer.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Mes yeux défaillent en cherchant ton salut, pour ta parole juste.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Traite ton serviteur selon ta bonté. Apprends-moi tes statuts.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Je suis ton serviteur. Donne-moi l'intelligence, pour que je connaisse vos témoignages.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Il est temps d'agir, Yahvé, car ils violent ta loi.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
C'est pourquoi j'aime tes commandements plus que l'or, oui, plus que de l'or pur.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
C'est pourquoi je considère que tous tes préceptes sont justes. Je déteste toutes les fausses routes.
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
PE Vos témoignages sont merveilleux, c'est pourquoi mon âme les garde.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
L'entrée de vos paroles donne de la lumière. Il donne de la compréhension aux simples.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
J'ai ouvert la bouche en grand et j'ai haleté, car je me languissais de tes commandements.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Tournez-vous vers moi, et ayez pitié de moi, comme tu le fais toujours à ceux qui aiment ton nom.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Établis mes pas dans ta parole. Ne laisse pas l'iniquité dominer sur moi.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Délivre-moi de l'oppression de l'homme, alors j'observerai tes préceptes.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Fais briller ton visage sur ton serviteur. Apprends-moi tes statuts.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Des ruisseaux de larmes coulent dans mes yeux, parce qu'ils n'observent pas ta loi.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
TZADHE Tu es juste, Yahvé. Vos jugements sont justes.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
Tu as commandé tes statuts avec justice. Ils sont entièrement dignes de confiance.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Mon zèle m'épuise, parce que mes ennemis ignorent vos paroles.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Vos promesses ont été testées de manière approfondie, et ton serviteur les aime.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Je suis petit et méprisé. Je n'oublie pas tes préceptes.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
Ta justice est une justice éternelle. Votre loi est la vérité.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
La détresse et l'angoisse se sont emparées de moi. Tes commandements sont mes délices.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
Tes témoignages sont justes à jamais. Donne-moi l'intelligence, pour que je puisse vivre.
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
QOPH J'ai appelé de tout mon cœur. Réponds-moi, Yahvé! Je garderai vos statuts.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
Je t'ai appelé. Sauve-moi! J'obéirai à tes statuts.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Je me lève avant l'aube et j'appelle à l'aide. Je mets mon espoir dans vos paroles.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mes yeux restent ouverts pendant les veilles de la nuit, pour que je puisse méditer sur ta parole.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Écoute ma voix, selon ta bonté. Ranime-moi, Yahvé, selon tes ordonnances.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Ils s'approchent, ceux qui suivent la méchanceté. Ils sont loin de votre loi.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Tu es proche, Yahvé. Tous tes commandements sont la vérité.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
Je le sais depuis longtemps grâce à vos témoignages, que tu les as fondés pour toujours.
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
RESH Considérez ma détresse, et délivrez-moi, car je n'oublie pas ta loi.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Plaidez ma cause, et rachetez-moi! Ranime-moi selon ta promesse.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
Le salut est loin des méchants, car ils ne cherchent pas tes statuts.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Grandes sont tes tendres compassions, Yahvé. Ranime-moi selon tes ordonnances.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Mes persécuteurs et mes adversaires sont nombreux. Je ne me suis pas écarté de vos témoignages.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Je regarde les infidèles avec dégoût, parce qu'ils n'observent pas ta parole.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Considérez combien j'aime vos préceptes. Ranime-moi, Yahvé, selon ta bonté.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
Toutes vos paroles sont vraies. Chacune de tes justes ordonnances est éternelle.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
SIN ET SHIN Les princes m'ont persécuté sans raison, mais mon cœur est en admiration devant vos mots.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Je me réjouis de ta parole, comme celui qui trouve un grand butin.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
Je déteste et abhorre le mensonge. J'aime votre loi.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Sept fois par jour, je te loue, à cause de vos justes ordonnances.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Ceux qui aiment ta loi ont une grande paix. Rien ne les fait trébucher.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
J'ai espéré en ton salut, Yahvé. J'ai appliqué tes commandements.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Mon âme a observé vos témoignages. Je les aime énormément.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
J'ai obéi à tes préceptes et à tes témoignages, car toutes mes voies sont devant toi.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
TAV Que mon cri parvienne jusqu'à toi, Yahvé. Donne-moi l'intelligence selon ta parole.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Que ma supplication vienne devant toi. Délivre-moi selon ta parole.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Que mes lèvres prononcent des louanges, car tu m'enseignes tes statuts.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Que ma langue chante ta parole, car tous tes commandements sont justes.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Que ta main soit prête à m'aider, car j'ai choisi tes préceptes.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
Je me suis langui de ton salut, Yahvé. Votre loi est mon plaisir.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Fais vivre mon âme, afin que je te loue. Que vos ordonnances m'aident.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Je me suis égaré comme une brebis égarée. Cherche ton serviteur, car je n'oublie pas tes commandements.

< Psalms 119 >