< Psalms 118 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Alabád a Jehová, porque es bueno; porque para siempre es su misericordia.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Diga ahora Israel: Que para siempre es su misericordia.
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Digan ahora la casa de Aarón: Que para siempre es su misericordia.
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
Digan ahora los que temen a Jehová: Que para siempre es su misericordia.
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
Desde la angustia llamé a Jehová; y Jehová me respondió con anchura.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
Jehová es por mí: no temeré lo que me haga el hombre.
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
Jehová es por mí entre los que me ayudan: por tanto yo veré venganza en los que me aborrecen.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
Mejor es esperar en Jehová, que esperar en hombre.
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
Mejor es esperar en Jehová, que esperar en príncipes.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
Todas las gentes me cercaron: en nombre de Jehová, que yo los talaré.
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
Cercáronme, y tornáronme a cercar: en nombre de Jehová, que yo los talaré.
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
Cercáronme como abejas, fueron apagados como fuego de espinos: en nombre de Jehová, que yo los talaré.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
Rempujando me rempujaste para que cayese: mas Jehová me ayudó.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
Mi fortaleza y mi canción es Jehová; y él me ha sido por salud.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
Voz de jubilación y de salud hay en las tiendas de los justos: la diestra de Jehová hace valentías.
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
La diestra de Jehová sublime: la diestra de Jehová hace valentías.
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
No moriré, mas viviré; y contaré las obras de Jehová.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
Castigando me castigó Jehová: mas no me entregó a la muerte.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Abrídme las puertas de la justicia: entraré por ellas, alabaré a Jehová.
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
Esta puerta de Jehová, los justos entrarán por ella.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
Alabarte he; porque me oíste; y me fuiste por salud.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
La piedra que desecharon los edificadores, ha sido por cabeza de esquina.
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
De parte de Jehová es esto, y es maravilla en nuestros ojos.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
Este es el día que hizo Jehová: gozarnos hemos y alegrarnos hemos en él.
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
Ruégote, o! Jehová, salva ahora: ruégote, o! Jehová, haz ahora prosperar.
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Bendito el que viene en nombre de Jehová: os bendecimos desde la casa de Jehová.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
Dios es Jehová, que nos ha resplandecido: atád víctimas con cuerdas a los cuernos del altar.
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
Dios mío eres tú, y a ti alabaré: Dios mío, a ti ensalzaré.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Alabád a Jehová, porque es bueno; porque para siempre es su misericordia.

< Psalms 118 >