< Psalms 118 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
E MILILANI aku ia Iehova; no ka mea, he maikai ia; A ua mau loa hoi kona lokomaikai.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
E olelo mai o ka Iseraela, Ua mau loa kona lokomaikai.
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
E olelo mai ka ohana a Aarona, Ua mau loa kona lokomaikai.
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
E olelo mai no ka poe e makau aku ia Iehova, Ua mau loa kona lokomaikai.
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
Maloko o ka pilikia, kahea aku au ia Iehova; A ae mai o Iehova ia'u ma kahi akea.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
O Iehova pu no me a'u, aole au e makau: Heaha ka mea a ke kanaka e hana mai ai ia'u?
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
O Iehova pu no me au, a me ka mea i kokua ia'u; A e nana ae au i ka poe inaina mai ia'u.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
Ua oi aku ka maikai o ka hilinai aku ia Iehova, Mamua o ka manao ana i ke kanaka.
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
Ua oi aku ka maikai o ka hilinai aku ia Iehova, Mamua o ka manao ana i na'lii.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
Hoopuni mai ko na aina a pau ia'u, Aka, ma ka inoa o Iehova, e luku aku ai au ia lakou.
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
Hoopuni mai no lakou ia'u, Oia, hoopuni mai no lakou ia'u; Aka, ma ka inoa o Iehova, e luku aku ai au ia lakou.
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
Hoopuni mai lakou ia'u, me he poe nalomeli la, Ua pio wale lakou, e like me ke ahi kakalaioa; No ka mea, ma ka inoa o Iehova wau e luku aku ai ia lakou.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
Ua hooke ikaika mai oe ia'u, i hina au; Aka, ua kokua mai o Iehova ia'u.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
O Iehova no ko'u ikaika, a me ko'u mea e hoolea ai, Ua lilo mai oia i Hoola no'u.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
Aia ka leo o ka hanoli, a me ka hoola, Ma na halelewa o ka poe pono: Ke hana koa nei ka lima akau o Iehova.
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
Ua hapaiia ka lima akau o Iehova a kiekie; Ke hana koa nei ka lima akau o Iehova.
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
Aole au e make, aka e ola aku no au, A e hoike aku au i ka hana a Iehova.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
Ua hahau nui mai o Iehova ia'u, Aole nae oia i haawi mai ia'u i ka make.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
E wehe mai oe i na pukapa o ka pono no'u, E komo aku no wau iloko olaila, A e mililani aku au ia Iehova.
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
O keia no ka pukapa o Iehova, E komo aku hoi ka poe pono iloko olaila.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
E mililani aku au ia oe, no ka mea, ua hoolohe mai oe ia'u, A ua lilo mai oe i hoola no'u.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
O ka pohaku a ka poe hana hale i haalele ai, Ua lilo ia i pohaku kumu no ke kihi.
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
Na Iehova mai no keia, A he mea mahaloia no hoi ia i ko kakou mau maka.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
O keia no ka la a Iehova i hana'i, E hauoli kakou, a e lealea ilaila.
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
Ke noi aku nei au ia oe, e Iehova, E hoola mai oe ano; Ke noi aku nei au ia oe, e Iehova, Ano oe e hoopomaikai mai.
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
E hoomaikaiia ka mea e hele mai ana ma ka inoa o Iehova; Ua hoomaikai aku makou ia oukou mailoko aku o ka hale o Iehova.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
O ke Akua no o Iehova, ua hoomalamalama mai oia ia kakou; E nakinaki i ka mohai i na kaula, Ma na pepeiaohao o ke kuahu.
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
O oe no ko'u Akua, e mililani aku au ia oe; O ko'u Akua no, e hapai aku au ia oe.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
E mililani aku ia Iehova, no ka mea, ua maikai oia; Ua mau loa hoi kona lokomaikai.