< Psalms 118 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Danket dem HERRN, denn er ist freundlich, ja, ewiglich währt seine Gnade!
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
So bekenne denn Israel: »Ja, ewiglich währt seine Gnade!«
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
So bekenne denn Aarons Haus: »Ja, ewiglich währt seine Gnade!«
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
So mögen denn alle Gottesfürcht’gen bekennen: »Ja, ewiglich währt seine Gnade!«
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
Aus meiner Bedrängnis rief ich zum HERRN: da hat der HERR mich erhört, mir weiten Raum geschafft.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
Ist der HERR für mich, so fürchte ich nichts: was können Menschen mir tun?
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
Tritt der HERR für mich zu meiner Hilfe ein, so werde ich siegreich jubeln über meine Feinde.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
Besser ist’s auf den HERRN vertrauen als auf Menschen sich verlassen;
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
besser ist’s auf den HERRN vertrauen als auf Fürsten sich verlassen.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
Die Heidenvölker alle hatten mich umringt: im Namen des HERRN, so vertilgte ich sie;
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
sie hatten mich umringt, umzingelt: im Namen des HERRN, so vertilgte ich sie;
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
sie hatten mich umringt wie Bienenschwärme; schnell wie ein Dornenfeuer sind sie erloschen: im Namen des HERRN, so vertilgte ich sie.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
Man hat mich hart gestoßen, damit ich fallen sollte, doch der HERR hat mir geholfen.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
Meine Stärke und mein Lobpreis ist der HERR, und er ist mein Retter geworden.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
Jubel und Siegeslieder erschallen in den Zelten der Gerechten: »Die Hand des HERRN schafft mächtige Taten,
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
die Hand des HERRN erhöht, die Hand des HERRN schafft mächtige Taten!«
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
Ich werde nicht sterben, nein, ich werde leben und die Taten des HERRN verkünden.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
Der HERR hat mich hart gezüchtigt, doch dem Tode mich nicht preisgegeben.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Öffnet mir die Tore der Gerechtigkeit: ich will durch sie eingehn, dem HERRN zu danken. –
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
Dies ist das Tor des HERRN: Gerechte dürfen hier eingehn. –
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
Ich danke dir, daß du mich erhört hast und bist mir ein Retter geworden.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
Der Stein, den die Bauleute verworfen haben, der ist zum Eckstein geworden;
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
vom HERRN ist dies geschehn, in unsern Augen ein Wunder!
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
Dies ist der Tag, den der HERR gemacht hat: laßt uns jubeln und fröhlich an ihm sein! –
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
Ach hilf doch, HERR, ach, HERR, laß wohl gelingen! –
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Gesegnet sei, der da kommt im Namen des HERRN! Wir segnen euch vom Hause des HERRN aus.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
Der HERR ist Gott, er hat uns Licht gegeben: schlinget den Reigen, mit Zweigen (geschmückt), bis an die Hörner des Altars!
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
Du bist mein Gott, ich will dir danken; mein Gott, ich will dich erheben!
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Danket dem HERRN, denn er ist freundlich, ja, ewiglich währt seine Gnade.