< Psalms 118 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
(Gesang der Festgemeinde auf dem Wege zum Tempelberg: ) / (1. Chor: ) / Danket Jahwe, denn er ist gütig, / (2. Chor: ) / Ja, ewig währet seine Huld.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
(1. Chor: ) / Es spreche Israel: / (2. Chor: ) / "Ja, ewig währet seine Huld."
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
(1. Chor: ) / Es spreche Aarons Haus: / (2. Chor: ) / "Ja, ewig währet seine Huld."
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
(1. Chor: ) / Es mögen alle sprechen, die Jahwe fürchten: / (2. Chor: ) / "Ja, ewig währet seine Huld."
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
(Der Chorführer allein im Namen der ganzen Festgemeinde: ) / Als ich aus der Bedrängnis Jahwe anrief, / Da erhörte mich Jah und machte mich frei.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
Ist Jahwe mit mir, so fürchte ich nichts: / Was können mir Menschen tun?
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
Tritt Jahwe für mich als Helfer auf, / So schau ich siegreich auf meine Hasser.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
(Eine Einzelstimme des Festchors: ) / Es ist besser, bei Jahwe Zuflucht zu suchen / (Der ganze Chor: ) / Als zu vertrauen auf Menschen.
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
(Eine Einzelstimme des Festchors: ) / Es ist besser, bei Jahwe Zuflucht zu suchen / (Der ganze Chor: ) / Als zu vertrauen auf Fürsten.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
(Der siegreiche Feldherr allein: ) / Es haben mich alle Heiden umringt, / Doch in Jahwes Namen zerhieb ich sie.
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
Sie haben mich umringt, ja immer wieder umringt; / Doch in Jahwes Namen zerhieb ich sie.
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
Sie haben mich sogar wie Bienen umringt, / Doch wie ein Dornenfeuer sind sie erloschen: / In Jahwes Namen zerhieb ich sie.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
Man hat mich zwar heftig gestoßen, damit ich käme zu Fall, / Doch Jahwe hat mir geholfen.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
Mein Sieg und mein Sang war Jah, / Er ward meine Rettung.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
(Eine Einzelstimme des Festchors: ) / Ein Jubel- und Siegesruf schallt in den Zelten der Frommen: / (Der ganze Festchor: ) / "Jahwes Rechte tut mächtige Taten.
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
Jahwes Recht ist hoch erhoben, / Jahwes Rechte tut mächtige Taten."
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
(Eine Einzelstimme des Festchors: ) / Ich werde nicht sterben, sondern leben / Und verkünden die Werke Jahs.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
(Der siegreiche Feldherr allein nach der Ankunft des Festzuges vor den Tempeltoren: ) / Hart zwar hat Jah mich gezüchtigt, / Aber dem Tod mich nicht preisgegeben.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Tut mir die Tore auf, durch die nur Gerechte ziehn; / Eingehn will ich in sie, ich will Jah danken!
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
Dies ist das Tor, das zu Jahwe führt: / Gerechte dürfen hier eingehn.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
(Der siegreiche Feldherr allein: ) / Dir dank ich, daß du mich erhört / Und mir Errettung gebracht hast.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
(Der Chor der Priester vom Tempel aus: ) / Der Stein, den die Bauleute verworfen haben, / Der ist zum Eckstein geworden.
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
(Der ganze Festchor: ) / Von Jahwe ist dies geschehn: / Wunderbar ist es in unsern Augen.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
(Der Chor der Priester: ) / Dies ist der Tag, den Jahwe gemacht. / Laßt uns jubeln und sein uns freun!
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
(Der ganze Festchor: ) / Ach, Jahwe, gewähre doch Hilfe! / Ach, Jahwe, gib doch Gedeihn!
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
(Der Chor der Priester antwortet darauf: ) / Gesegnet sei er, der da kommt, mit Jahwes Namen! / Wir haben euch gesegnet von Jahwes Tempel aus.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
(Der ganze Festchor: ) / Ein starker Gott ist Jahwe: er hat uns Licht gespendet. / (Der Chor der Priester: ) / Bindet die Opfertiere so zahlreich an mit Stricken, / (Daß sie den Vorhof füllen) / Bis an die Hörner des Altars!
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
(Der siegreiche Feldherr allein: ) / Mein starker Gott bist du: ich will dir danken. / Du bist mein Gott: dich will ich rühmen.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
(Der ganze Festchor und der Chor der Priester, also die ganze Festversammlung mit einem Munde: ) / Danket Jahwe, denn er ist gütig; / Ja, ewig währet seine Huld!