< Psalms 118 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Louez l’Éternel, car il est bon, Car sa miséricorde dure à toujours!
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Qu’Israël dise: Car sa miséricorde dure à toujours!
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Que la maison d’Aaron dise: Car sa miséricorde dure à toujours!
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
Que ceux qui craignent l’Éternel disent: Car sa miséricorde dure à toujours!
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
Du sein de la détresse j’ai invoqué l’Éternel: L’Éternel m’a exaucé, m’a mis au large.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
L’Éternel est pour moi, je ne crains rien: Que peuvent me faire des hommes?
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
L’Éternel est mon secours, Et je me réjouis à la vue de mes ennemis.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
Mieux vaut chercher un refuge en l’Éternel Que de se confier à l’homme;
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
Mieux vaut chercher un refuge en l’Éternel Que de se confier aux grands.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
Toutes les nations m’environnaient: Au nom de l’Éternel, je les taille en pièces.
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
Elles m’environnaient, m’enveloppaient: Au nom de l’Éternel, je les taille en pièces.
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
Elles m’environnaient comme des abeilles; Elles s’éteignent comme un feu d’épines; Au nom de l’Éternel, je les taille en pièces.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
Tu me poussais pour me faire tomber; Mais l’Éternel m’a secouru.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
L’Éternel est ma force et le sujet de mes louanges; C’est lui qui m’a sauvé.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
Des cris de triomphe et de salut s’élèvent dans les tentes des justes: La droite de l’Éternel manifeste sa puissance!
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
La droite de l’Éternel est élevée! La droite de l’Éternel manifeste sa puissance!
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
Je ne mourrai pas, je vivrai, Et je raconterai les œuvres de l’Éternel.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
L’Éternel m’a châtié, Mais il ne m’a pas livré à la mort.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Ouvrez-moi les portes de la justice: J’entrerai, je louerai l’Éternel.
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
Voici la porte de l’Éternel: C’est par elle qu’entrent les justes.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
Je te loue, parce que tu m’as exaucé, Parce que tu m’as sauvé.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
La pierre qu’ont rejetée ceux qui bâtissaient Est devenue la principale de l’angle.
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
C’est de l’Éternel que cela est venu: C’est un prodige à nos yeux.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
C’est ici la journée que l’Éternel a faite: Qu’elle soit pour nous un sujet d’allégresse et de joie!
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
O Éternel, accorde le salut! O Éternel, donne la prospérité!
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Béni soit celui qui vient au nom de l’Éternel! Nous vous bénissons de la maison de l’Éternel.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
L’Éternel est Dieu, et il nous éclaire. Attachez la victime avec des liens, Amenez-la jusqu’aux cornes de l’autel!
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
Tu es mon Dieu, et je te louerai; Mon Dieu! Je t’exalterai.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Louez l’Éternel, car il est bon, Car sa miséricorde dure à toujours!

< Psalms 118 >