< Psalms 118 >
1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Alléluiah! Rendez gloire au Seigneur, parce qu'il est bon, et que sa miséricorde est éternelle.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Que la maison d'Israël dise qu'il est bon, et sa miséricorde éternelle.
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Que la maison d'Aaron dise qu'il est bon, et sa miséricorde éternelle.
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
Que tous ceux qui craignent le Seigneur disent qu'il est bon, et sa miséricorde éternelle.
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
Dans la tribulation j'ai invoqué le Seigneur, et il m'a exaucé, et il m'a mis au large.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
Que le Seigneur soit mon champion, et je ne craindrai rien de ce que l'homme peut me faire.
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
Que le Seigneur soit mon champion, et moi je mépriserai mes ennemis.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
Mieux vaut se confier au Seigneur que se confier à l'homme.
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
Mieux vaut espérer dans le Seigneur qu'espérer dans les princes.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
Toutes les nations m'avaient environné; mais, au nom du Seigneur, je les ai repoussées.
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
Elles m'avaient enfermé dans un cercle pour m'envelopper; mais, au nom du Seigneur, je les ai repoussées.
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
Elles se pressaient autour de moi comme des abeilles autour d'un rayon de miel; elles lançaient des flammes, comme des épines en feu; mais, au nom du Seigneur, je les ai repoussées.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
À leur choc j'ai craint de tomber, et le Seigneur m'a secouru.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
Le Seigneur est ma force et ma louange; c'est lui qui m'a sauvé.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
La voix de l'allégresse et du salut est sous les tentes des justes; la droite du Seigneur a fait œuvre de puissance.
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
La droite du Seigneur m'a élevé; la droite du Seigneur a fait œuvre de puissance.
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
Je ne mourrai point; mais je vivrai et je raconterai les œuvres du Seigneur.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
Le Seigneur m'a châtié pour me corriger; mais il ne m'a point livré à la mort.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Ouvrez-moi les portes de la justice, et je les franchirai, et je rendrai gloire au Seigneur.
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
C'est la porte du Seigneur, c'est par elle que les justes entreront.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
Je te rendrai gloire, parce que tu m'as exaucé, et que tu as été mon salut.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
La pierre que les constructeurs avaient rejetée est devenue la pierre angulaire de l'édifice.
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
C'est le Seigneur qui a fait cela, et nos yeux en sont émerveillés.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
Voici le jour qu'a fait le Seigneur; tressaillons et réjouissons-nous en ce jour.
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
Seigneur, sauve-moi; Seigneur, fais-moi prospérer.
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Béni soit celui qui vient au nom du Seigneur. Nous vous avons bénis de la maison du Seigneur.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
Dieu, c'est le Seigneur; il a brillé à nos yeux: célébrez une fête solennelle avec des rameaux touffus, et ombragez jusqu'aux cornes de l'autel.
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
Tu es mon Dieu, et je te rendrai gloire; tu es mon Dieu, et je t'exalterai; je te rendrai gloire, parce que tu m'as exaucé, et que tu as été mon salut.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Rendez gloire au Seigneur, parce qu'il est bon, et que sa miséricorde est éternelle.