< Psalms 118 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Give ye thanks to Yahweh—For he is good, For, age-abiding, is his lovingkindness.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
I pray you! let Israel, say, For, age-abiding, is his lovingkindness.
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
I pray you! let the house of Aaron, say, For, age-abiding, is his lovingkindness.
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
I pray you! let them who revere Yahweh, say, For, age-abiding, is his lovingkindness.
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
Out of a strait, called I on Yah, He answered me with enlargement.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
Yahweh, is on my side, I will not fear, What can man, do unto me?
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
Yahweh, is on my side, with them who help me, I, therefore shall gaze upon them who hate me.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
It is, better to seek refuge in Yahweh, than to put confidence in man:
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
It is, better to seek refuge in Yahweh, than to put confidence in nobles.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
All nations, have compassed me about, In the Name of Yahweh, surely I will make them be circumcised;
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
They have compassed me about—yea compassed me about, In the Name of Yahweh, surely I will make them be circumcised;
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
They have compassed me about like wax bees, they have blazed up like the fire of thorns, In the Name of Yahweh, surely I will make them be circumcised.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
Thou didst, thrust sore, at me that I might fall, But, Yahweh, hath helped me.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
My might and melody, is Yah, and he hath become mine by salvation.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
The voice of shouting and salvation, is in the tents of the righteous, The right hand of Yahweh, is doing valiantly:
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
The right hand of Yahweh, is exalted, The right hand of Yahweh, is doing valiantly.
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
I shall not die, but live, That I may recount the doings of Yah.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
Yah, chastened me sore, But, unto death, did not deliver me.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Open to me the gates of righteousness, I will enter therein, I will give thanks unto Yah.
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
This, is the gate for Yahweh, Such as are righteous, shall enter therein.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
I will thank thee, because thou hast answered me, And hast become mine, by salvation.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
A stone the builders refused, hath become the head of the corner:
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
From Yahweh, hath this come to pass, The same, is marvellous in our eyes.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
This is the day, which Yahweh hath made, We will exult, and be glad therein.
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
Ah now, Yahweh, do save, we beseech thee, Ah now, Yahweh, do send success, we beseech thee!
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Blessed be he that entereth, In the Name of Yahweh, we have blessed you, out of the house of Yahweh.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
Yahweh is GOD, and hath shed on us light, —Bind ye the festal sacrifice with cords, Up to the horns of the altar.
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
My GOD, thou art, and I will thank thee, —My Elohim, I will exalt thee.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Give ye thanks to Yahweh—For he is good, For, age-abiding, is his lovingkindness.

< Psalms 118 >