< Psalms 118 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
O give thanks to the LORD; for he is good: because his mercy endures for ever.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Let Israel now say, that his mercy endures for ever.
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Let the house of Aaron now say, that his mercy endures for ever.
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
Let them now that fear the LORD say, that his mercy endures for ever.
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
I called on the LORD in distress: the LORD answered me, and set me in a large place.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
The LORD is on my side; I will not fear: what can man do to me?
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
The LORD takes my part with them that help me: therefore shall I see my desire on them that hate me.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
It is better to trust in the LORD than to put confidence in man.
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
It is better to trust in the LORD than to put confidence in princes.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
All nations compassed me about: but in the name of the LORD will I destroy them.
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
They compassed me about; yes, they compassed me about: but in the name of the LORD I will destroy them.
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
They compassed me about like bees: they are quenched as the fire of thorns: for in the name of the LORD I will destroy them.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
You have thrust sore at me that I might fall: but the LORD helped me.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
The LORD is my strength and song, and is become my salvation.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
The voice of rejoicing and salvation is in the tabernacles of the righteous: the right hand of the LORD does valiantly.
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
The right hand of the LORD is exalted: the right hand of the LORD does valiantly.
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
I shall not die, but live, and declare the works of the LORD.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
The LORD has chastened me sore: but he has not given me over to death.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Open to me the gates of righteousness: I will go into them, and I will praise the LORD:
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
This gate of the LORD, into which the righteous shall enter.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
I will praise you: for you have heard me, and are become my salvation.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
The stone which the builders refused is become the head stone of the corner.
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
This is the LORD’s doing; it is marvelous in our eyes.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
This is the day which the LORD has made; we will rejoice and be glad in it.
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
Save now, I beseech you, O LORD: O LORD, I beseech you, send now prosperity.
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Blessed be he that comes in the name of the LORD: we have blessed you out of the house of the LORD.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
God is the LORD, which has showed us light: bind the sacrifice with cords, even to the horns of the altar.
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
You are my God, and I will praise you: you are my God, I will exalt you.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
O give thanks to the LORD; for he is good: for his mercy endures for ever.

< Psalms 118 >