< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
Amo o SENHOR, porque ele escuta minha voz [e] minhas súplicas.
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
Porque ele tem inclinado a mim seus ouvidos; por isso eu clamarei a ele em [todos] os meus dias.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
Cordas da morte me cercaram, e angústias do Xeol me afrontaram; encontrei opressão e aflição. (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Mas clamei ao nome do SENHOR, [dizendo]: Ah SENHOR, livra minha alma!
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
O SENHOR é piedoso e justo; e nosso Deus é misericordioso.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
O SENHOR protege os simples; eu estava com graves problemas, mas ele me livrou.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Minha alma, volta ao teu descanso, pois o SENHOR tem te tratado bem.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
Porque tu, [SENHOR], livraste minha alma da morte, meus olhos das lágrimas, e meu pé do tropeço.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Andarei diante do SENHOR na terra dos viventes.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
Eu cri, por isso falei; estive muito aflito.
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
Eu dizia em minha pressa: Todo homem é mentiroso.
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
O que pagarei ao SENHOR por todos os benefícios dele para mim?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
Tomarei o copo da salvação, [e] chamarei o nome do SENHOR.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Certamente pagarei meus votos ao SENHOR, na presença de todo o seu povo.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Preciosa é aos olhos do SENHOR a morte de seus santos.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
Ah SENHOR, verdadeiramente eu sou teu servo; sou teu servo, filho de tua serva; tu me soltaste das correntes que me prendiam.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
Sacrificarei a ti sacrifício de agradecimento, e chamarei o nome do SENHOR.
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
Certamente pagarei meus votos ao SENHOR, na presença de todo o seu povo;
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
Nos pátios da casa do SENHOR, em meio de ti, ó Jerusalém. Aleluia!

< Psalms 116 >