< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
Miłuję PANA, bo usłyszał mój głos i moje prośby.
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
Nakłonił bowiem swego ucha ku mnie, dlatego będę go wzywał za moich dni.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
Otoczyły mnie boleści śmierci, utrapienia piekła przeniknęły mnie; przyszły na mnie ucisk i boleść. (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Wtedy wezwałem imienia PANA, [mówiąc]: PANIE, proszę, wybaw moją duszę.
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Łaskawy jest PAN i sprawiedliwy, nasz Bóg jest miłosierny.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
PAN strzeże ludzi prostych; byłem uciśniony, a wybawił mnie.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Powróć, moja duszo, do swego odpoczynku, bo PAN dobrze ci uczynił.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
Wybawił bowiem moją duszę od śmierci, oczy moje od płaczu, moją nogę od upadku.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Będę chodził przed obliczem PANA w ziemi żyjących.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
Uwierzyłem i dlatego przemówiłem; byłem bardzo strapiony.
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
Powiedziałem w zatrwożeniu: Każdy człowiek to kłamca.
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
Cóż oddam PANU za wszystkie jego dobrodziejstwa, które mi [wyświadczył]?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
Wezmę kielich zbawienia i będę wzywać imienia PANA.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Moje śluby złożone PANU wypełnię teraz przed całym jego ludem.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Cenna jest w oczach PANA śmierć jego świętych.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
O PANIE, jestem twoim sługą; jestem twoim sługą i synem twojej służącej; rozerwałeś moje więzy.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
Tobie złożę ofiarę chwały i będę wzywać imienia PANA.
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
Moje śluby złożone PANU wypełnię teraz przed całym jego ludem;
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
W dziedzińcach domu PANA, pośrodku ciebie, Jeruzalem! Alleluja.

< Psalms 116 >