< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
Eg elskar Herren, for han høyrer mi røyst, mine bøner.
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
For han hev bøygt sitt øyra til meg, og alle mine dagar vil eg kalla på honom.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
Daude-band hadde spent seg um meg, helheims trengsla hadde funne meg; naud og sorg fann eg. (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Men eg kalla på Herrens namn: «Å Herre, berga mi sjæl!»
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Herren er nådig og rettferdig, og vår Gud er miskunnsam.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
Herren varar dei einfalde, eg var ein arming, og han frelste meg.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Kom attende, mi sjæl, til di ro! for Herren hev gjort vel imot deg.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
Ja, du fria mi sjæl frå dauden, mitt auga frå tåror, min fot frå fall.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Eg skal vandra for Herrens åsyn i landi åt dei livande.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
Eg trudde, for eg tala; eg var i stor plåga.
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
Eg sagde i min ræddhug: «Kvar mann er ein ljugar!»
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
Kva skal eg gjeva Herren att for alle hans velgjerningar imot meg?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
Eg vil lyfta frelse-staupet, og Herrens namn vil eg påkalla.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Mine lovnader vil eg halda for Herren, og det for augo på alt hans folk.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Dyr er i Herrens augo dauden åt hans heilage.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
Å Herre, eg er din tenar, veit du, eg er din tenar, son åt di tenestkvinna; du hev løyst mine band.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
Til deg vil eg ofra takkoffer, og Herrens namn vil eg påkalla.
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
Mine lovnader vil eg halda for Herren, og det for augo på alt hans folk,
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
i fyregardarne til Herrens hus, midt i deg, Jerusalem. Halleluja!

< Psalms 116 >