< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
Das ist mir lieb, daß der HERR meine Stimme und mein Flehen höret,
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
daß er sein Ohr zu mir neiget; darum will ich mein Leben lang ihn anrufen.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
Stricke des Todes hatten mich umfangen, und Angst der Hölle hatte mich getroffen; ich kam in Jammer und Not (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Aber ich rief an den Namen des HERRN: O HERR, errette meine Seele!
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Der HERR ist gnädig und gerecht, und unser Gott ist barmherzig.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
Der HERR behütet die Einfältigen. Wenn ich unterliege, so hilft er mir.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Sei nun wieder zufrieden, meine Seele; denn der HERR tut dir Gutes.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
Denn du hast meine Seele aus dem Tode gerissen, mein Auge von den Tränen, meinen Fuß vom Gleiten.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Ich will wandeln vor dem HERRN im Lande der Lebendigen.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
Ich glaube, darum rede ich. Ich werde aber sehr geplagt.
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
Ich sprach in meinem Zagen: Alle Menschen sind Lügner.
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
Wie soll ich dem HERRN vergelten alle seine Wohltat, die er an mir tut?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
Ich will den heilsamen Kelch nehmen und des HERRN Namen predigen.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Ich will meine Gelübde dem HERRN bezahlen vor all seinem Volk.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Der Tod seiner Heiligen ist wert gehalten vor dem HERRN.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
O HERR, ich bin dein Knecht; ich bin dein Knecht, deiner Magd Sohn. Du hast meine Bande zerrissen.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
Dir will ich Dank opfern und des HERRN Namen predigen.
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
Ich will meine Gelübde dem HERRN bezahlen vor all seinem Volk,
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
in den Höfen am Hause des HERRN, in dir, Jerusalem. Halleluja!

< Psalms 116 >