< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
C'est mon bonheur que l'Éternel écoute ma voix, mes prières!
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
Car Il a penché vers moi son oreille; aussi toute ma vie je veux l'invoquer.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
Les liens de la mort m'enveloppaient, j'étais atteint des angoisses des Enfers, je trouvais devant moi la détresse et la douleur. (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Mais j'invoquai le nom de l'Éternel: « O Etemel, sauve mon âme! »
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
L'Éternel est clément et juste, et notre Dieu, plein de miséricorde.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
L'Éternel garde les simples; j'étais affligé, et Il me fut secourable.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Rentre, mon âme, dans ton repos! car l'Éternel t'a fait du bien.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
Car Tu as affranchi mon âme de la mort, mes yeux des pleurs, mon pied de la chute.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Je marcherai sous le regard de l'Éternel, sur la terre des vivants.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
J'ai cru, car j'ai parlé. J'avais beaucoup à souffrir!
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
Je disais dans mes alarmes: « Tous les hommes sont trompeurs. »
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
Comment rendrai-je à l'Éternel tous les bienfaits que j'ai reçus de lui?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
J'élèverai la coupe des délivrances, et j'invoquerai le nom de l'Éternel;
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
j'accomplirai mes vœux envers l'Éternel à la face de tout son peuple.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Aux yeux de l'Éternel, ce qui coûte, c'est la mort de ses bien-aimés.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
O exauce-moi, Éternel! car je suis ton serviteur, le fils de ta servante. Tu as détaché mes chaînes;
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
je t'offrirai le sacrifice de la reconnaissance, et j'invoquerai le nom de l'Éternel;
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
j'accomplirai mes vœux envers l'Éternel, à la face de tout son peuple,
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
dans les parvis de la maison de l'Éternel, dans ton sein, ô Jérusalem! Alléluia!

< Psalms 116 >