< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
I 'ahav ·affectionately love· Adonai, because he sh'ma ·hears obeys· my voice, and my cries for mercy.
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
Because he has turned his ear to me, therefore I will call on him as long as I live.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
The cords of death surrounded me, the pains of Sheol ·Place of the dead· got a hold of me. I found trouble and sorrow. (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Then I called on Adonai’s name: “Adonai, I beg you, deliver my soul.”
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Adonai is gracious and righteous. Yes, our God is racham ·merciful love·.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
Adonai preserves the simple. I was brought low, and he saved me.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Teshuvah ·Completely return· to your rest, my soul, for Adonai has dealt bountifully with you.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
For you have delivered my soul from death, my eyes from tears, and my feet from falling.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
I will walk before Adonai in the land of the living.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
I believed, therefore I said, “I was greatly afflicted.”
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
I said in my haste, “All men are liars.”
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
What will I give to Adonai for all his benefits toward me?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
I will take the cup of yishu'ah ·salvation·, and call on Adonai’s name.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
I will pay my vows to Adonai, yes, in the presence of all his people.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Precious in Adonai’s sight is the death of his saints.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
Adonai, truly I am your servant. I am your servant, the son of your servant. You have freed me from my chains.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
I will offer to you the sacrifice of thanksgiving, and will call on Adonai’s name.
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
I will pay my vows to Adonai, yes, in the presence of all his people,
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
in the courts of Adonai’s house, in the middle of you, Jerusalem [City of peace]. Halleluyah ·praise Yah·!

< Psalms 116 >