< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
I rejoice that the LORD hath heard the voice of my supplication,
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
That he hath inclined his ear to me and heard me; I will call upon him as long as I live.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
The snares of death encompassed me, And the pains of the underworld seized upon me; I found distress and sorrow. (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Then called I upon the LORD: O LORD! deliver me!
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Gracious is the LORD, and righteous; Yea, our God is merciful.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
The LORD preserveth the simple; I was brought low, and he helped me.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Return, O my soul! to thy rest! For the LORD hath dealt kindly with thee.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
For thou hast preserved me from death; Thou hast kept mine eyes from tears, And my feet from falling!
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
I shall walk before the LORD, In the land of the living.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
I had trust, although I said, “I am grievously afflicted!”
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
I said in my distress, “All men are liars.”
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
What shall I render to the LORD For all his benefits to me?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
I will take the cup of salvation, And call upon the name of the LORD;
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
I will pay my vows to the LORD, In the presence of all his people.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Precious in the eyes of the LORD Is the death of his holy ones.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
Hear, O LORD! for I am thy servant; I am thy servant, the son of thy handmaid! Thou hast loosed my bonds.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
I will offer to thee the sacrifice of thanksgiving, And will call upon the name of the LORD.
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
I will pay my vows to the LORD In the presence of all his people,
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
In the courts of the house of the LORD, In the midst of thee, O Jerusalem! Praise ye the LORD!

< Psalms 116 >