< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
I love Yhwh, because he hath heard my voice and my supplications.
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
Because he hath inclined his ear unto me, therefore will I call upon him as long as I live.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
The sorrows of death compassed me, and the pains of hell gat hold upon me: I found trouble and sorrow. (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Then called I upon the name of Yhwh; O Yhwh, I beseech thee, deliver my soul.
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Gracious is Yhwh, and righteous; yea, our God is merciful.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
Yhwh preserveth the simple: I was brought low, and he helped me.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Return unto thy rest, O my soul; for Yhwh hath dealt bountifully with thee.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
For thou hast delivered my soul from death, mine eyes from tears, and my feet from falling.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
I will walk before Yhwh in the land of the living.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
I believed, therefore have I spoken: I was greatly afflicted:
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
I said in my haste, All men are liars.
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
What shall I render unto Yhwh for all his benefits toward me?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
I will take the cup of salvation, and call upon the name of Yhwh.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
I will pay my vows unto Yhwh now in the presence of all his people.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Precious in the sight of Yhwh is the death of his saints.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
O Yhwh, truly I am thy servant; I am thy servant, and the son of thine handmaid: thou hast loosed my bonds.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
I will offer to thee the sacrifice of thanksgiving, and will call upon the name of Yhwh.
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
I will pay my vows unto Yhwh now in the presence of all his people,
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
In the courts of Yhwh's house, in the midst of thee, O Jerusalem. Hallelu jah.

< Psalms 116 >