< Psalms 116 >
1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
I love that the LORD should hear my voice and my supplications.
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
Because He hath inclined His ear unto me, therefore will I call upon Him all my days.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol )
The cords of death compassed me, and the straits of the nether-world got hold upon me; I found trouble and sorrow. (Sheol )
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
But I called upon the name of the LORD: 'I beseech thee, O LORD, deliver my soul.'
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Gracious is the LORD, and righteous; yea, our God is compassionate.
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
The LORD preserveth the simple; I was brought low, and He saved me.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Return, O my soul, unto Thy rest; for the LORD hath dealt bountifully with thee.
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
For thou hast delivered my soul from death, mine eyes from tears, and my feet from stumbling.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
I shall walk before the LORD in the lands of the living.
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
I trusted even when I spoke: 'I am greatly afflicted.'
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
I said in my haste: 'All men are liars.'
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
How can I repay unto the LORD all His bountiful dealings toward me?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
I will lift up the cup of salvation, and call upon the name of the LORD.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
My vows will I pay unto the LORD, yea, in the presence of all His people.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Precious in the sight of the LORD is the death of His saints.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
I beseech Thee, O LORD, for I am Thy servant; I am Thy servant, the son of Thy handmaid; Thou hast loosed my bands.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
I will offer to thee the sacrifice of thanksgiving, and will call upon the name of the LORD.
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
I will pay my vows unto the LORD, yea, in the presence of all His people;
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
In the courts of the LORD'S house, in the midst of thee, O Jerusalem. Hallelujah.