< Psalms 116 >

1 Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
Halleluja! Jeg elsker HERREN, thi han hører min Røst, min tryglende Bøn,
2 Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
ja, han bøjed sit Øre til mig, jeg paakaldte HERRENS Navn.
3 Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
Dødens Baand omspændte mig, Dødsrigets Angster greb mig, i Trængsel og Nød var jeg stedt. (Sheol h7585)
4 Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
Jeg paakaldte HERRENS Navn: »Ak, HERRE, frels min Sjæl!«
5 Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
Naadig er HERREN og retfærdig, barmhjertig, det er vor Gud;
6 Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
HERREN vogter enfoldige, jeg var ringe, dog frelste han mig.
7 Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
Vend tilbage, min Sjæl, til din Ro, thi HERREN har gjort vel imod dig!
8 Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
Ja, han fried min Sjæl fra Døden, mit Øje fra Graad, min Fod fra Fald.
9 nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Jeg vandrer for HERRENS Aasyn udi de levendes Land;
10 Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
jeg troede, derfor talte jeg, saare elendig var jeg,
11 Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
sagde saa i min Angst: »Alle Mennesker lyver!«
12 Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
Hvorledes skal jeg gengælde HERREN alle hans Velgerninger mod mig?
13 Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
Jeg vil løfte Frelsens Bæger og paakalde HERRENS Navn.
14 Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
Jeg vil indfri HERREN mine Løfter i Paasyn af alt hans Folk.
15 Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
Kostbar i HERRENS Øjne er hans frommes Død.
16 Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
Ak, HERRE, jeg er jo din Tjener, din Tjener, din Tjenerindes Søn, mine Lænker har du løst.
17 Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
Jeg vil ofre dig Lovprisningsoffer og paakalde HERRENS Navn;
18 Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
mine Løfter vil jeg indfri HERREN i Paasyn af alt hans Folk
19 nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.
i HERRENS Hus's Forgaarde og i din Midte, Jerusalem!

< Psalms 116 >