< Psalms 115 >
1 Kì í ṣe fún wa, Olúwa kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
Icke åt oss, HERRE, icke åt oss, utan åt ditt namn giv äran, för din nåds, för din sannings skull.
2 Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.
Varför skulle hedningarna få säga: "Var är nu deras Gud?"
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
Vår Gud är ju i himmelen; han kan göra allt vad han vill.
4 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
Men deras avgudar äro silver och guld, verk av människohänder.
5 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
De hava mun och tala icke, de hava ögon och se icke,
6 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
de hava öron och höra icke, de hava näsa och lukta icke.
7 Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
Med sina händer taga de icke, med sina fötter gå de icke; de hava intet ljud i sin strupe.
8 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
De som hava gjort dem skola bliva dem lika, ja, alla som förtrösta på dem.
9 Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
I av Israel, förtrösten på HERREN. Ja, han är deras hjälp och sköld.
10 Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
I av Arons hus, förtrösten på HERREN. Ja, han är deras hjälp och sköld.
11 Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
I som frukten HERREN, förtrösten på HERREN. Ja, han är deras hjälp och sköld.
12 Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni.
HERREN har tänkt på oss, han skall välsigna, han skall välsigna Israels hus, han skall välsigna Arons hus,
13 Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, àti kékeré àti ńlá.
han skall välsigna dem som frukta HERREN, de små såväl som de stora.
14 Olúwa yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Ja, HERREN föröke eder, seder själva och edra barn.
15 Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Varen välsignade av HERREN, av honom som har gjort himmel och jord.
16 Ọ̀run àní ọ̀run ni ti Olúwa: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
Himmelen är HERRENS himmel, och jorden har han givit åt människors barn.
17 Òkú kò lè yìn Olúwa, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
De döda prisa icke HERREN, ingen som har farit ned i det tysta.
18 Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún Olúwa láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin Olúwa.
Men vi, vi skola lova HERREN från nu och till evig tid. Halleluja!