< Psalms 115 >

1 Kì í ṣe fún wa, Olúwa kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
Nie nam, PANIE, nie nam, ale twemu imieniu daj chwałę za twoje miłosierdzie [i] prawdę.
2 Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.
Czemu mają mówić poganie: Gdzież teraz [jest] ich Bóg?
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
A nasz Bóg [jest] w niebie, czyni wszystko, co zechce.
4 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
Ich bożki [to] srebro i złoto, dzieło rąk ludzkich.
5 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
Usta mają, ale nie mówią; mają oczy, ale nie widzą.
6 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
Uszy mają, ale nie słyszą; mają nozdrza, ale nie czują.
7 Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
Ręce mają, ale nie dotykają; mają nogi, ale nie chodzą; ani gardłem swoim nie wydają głosu.
8 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Niech będą do nich podobni ci, którzy je robią, [i] wszyscy, którzy im ufają.
9 Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
Izraelu, ufaj PANU; on jest ich pomocą i tarczą.
10 Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
Domu Aarona, ufaj PANU; on jest ich pomocą i tarczą.
11 Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
Wy, którzy się boicie PANA, ufajcie PANU; on jest ich pomocą i tarczą.
12 Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni.
PAN pamięta o nas, będzie błogosławił; będzie błogosławił domowi Izraela, będzie błogosławił domowi Aarona.
13 Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, àti kékeré àti ńlá.
Będzie błogosławił tym, którzy boją się PANA, i małym, i wielkim.
14 Olúwa yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
Rozmnoży was PAN, was i waszych synów.
15 Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Błogosławieni jesteście przez PANA, który stworzył niebo i ziemię.
16 Ọ̀run àní ọ̀run ni ti Olúwa: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
Niebiosa są niebiosami PANA, ale ziemię dał synom ludzkim.
17 Òkú kò lè yìn Olúwa, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
Umarli nie będą chwalili PANA ani nikt z tych, którzy zstępują do [miejsca] milczenia.
18 Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún Olúwa láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin Olúwa.
Ale my będziemy błogosławili PANA, odtąd aż na wieki. Alleluja.

< Psalms 115 >