< Psalms 115 >

1 Kì í ṣe fún wa, Olúwa kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
A OLE ia makou, e Iehova, aole ia makou, Aka. i kou inoa no e haawiia'ka ai ka hoonani. No kou lokomaikai, a me kou oiaio.
2 Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.
No ke aha la i olelo mai ai ko na aina e, Aubea ko lakou Akua?
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
Aia no i ka lani ko makou Akua; Ua haua no oia i na mea a pau ana i makemake ai.
4 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
O ko lakou poe akua, he kala, a he gula hoi, O ka haua a na lima o kanaka.
5 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
He waha no ko lakou, aole nae e olelo mai; He maka no ko lakou, aole nae e ike mai:
6 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
He pepeiao no ko lakou, aole nae e lohe; He ihu no hoi ko lakou, aole nae e honi:
7 Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
He mau lima no ko lakou, aole nae e lawelawe; He mau wawae no ko lakou, aole nae e hele; Aole hoi e olelo lakou, ma ko lakou kania-i.
8 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Me ia poe akua, pela no ka poe i hana ia lakou, A me ka poe a pau e hilinai ia lakou.
9 Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
E ka Iseraela, e hilinai oukou ia Iehova; Oia ko lakou kokua a me ko lakou palekaua.
10 Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
E ka ohana a Aarona, e hilinai oukou ia Iehova; Oia ko lakou kokua, a me ko lakou palekaua.
11 Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
E ka poe makau ia Iehova, e hilinai oukou ia Iehova; Oia ko lakou kokua, a me ko lakou palekaua.
12 Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni.
Ua hoomanao mai o Iehova ia kakou, e hoomaikai no oia; E hoomaikai mai no oia i ka ohana a Iseraela, E hoomaikai mai no oia i ka ohana a Aarona.
13 Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, àti kékeré àti ńlá.
E hoomaikai mai no oia i ka poe e makau aku ia Iehova, I na mea uuku, a me na mea nui.
14 Olúwa yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
E hoomahuahua mai no o Iehova ia oukou, Ia oukou no, a me ka oukou poe keiki.
15 Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Ua hoopomaikaiia oukou e Iehova, Ka mea nana i hana ka lani, a me ka honua.
16 Ọ̀run àní ọ̀run ni ti Olúwa: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
Na Iehova no na lani o na lani; Ua haawi mai nae oia i ka honua no na keiki a kanaka.
17 Òkú kò lè yìn Olúwa, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
Aole ka poe make e halelu aku ia Iehova, Aole hoi ka poe a pau e iho ilalo i kahi ekemu ole.
18 Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún Olúwa láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin Olúwa.
Aka, o kakou, e hoomaikai aku no kakou ia Iehova, Mai keia wa aku, a i ka manawa pau ole. E halelu aku oukou ia Iehova,

< Psalms 115 >