< Psalms 115 >

1 Kì í ṣe fún wa, Olúwa kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
Lord, not to vs, not to vs; but yyue thou glorie to thi name.
2 Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.
On thi merci and thi treuthe; lest ony tyme hethene men seien, Where is the God of hem?
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
Forsothe oure God in heuene; dide alle thingis, whiche euere he wolde.
4 Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
The symulacris of hethene men ben siluer and gold; the werkis of mennus hondis.
5 Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
Tho han mouth, and schulen not speke; tho han iyen, and schulen not se.
6 Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
Tho han eeris, and schulen not here; tho han nose thurls, and schulen not smelle.
7 Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
Tho han hondis, and schulen not grope; tho han feet, and schulen not go; tho schulen not crye in her throte.
8 Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
Thei that maken tho ben maad lijk tho; and alle that triste in tho.
9 Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
The hous of Israel hopide in the Lord; he is the helpere `of hem, and the defendere of hem.
10 Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
The hous of Aaron hopide in the Lord; he is the helpere of hem, and the defendere of hem.
11 Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
Thei that dreden the Lord, hopiden in the Lord; he is the helpere of hem, and the defendere of hem.
12 Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni.
The Lord was myndeful of vs; and blesside vs. He blesside the hous of Israel; he blesside the hous of Aaron.
13 Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, àti kékeré àti ńlá.
He blesside alle men that dreden the Lord; `he blesside litle `men with the grettere.
14 Olúwa yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
The Lord encreesse on you; on you and on youre sones.
15 Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
Blessid be ye of the Lord; that made heuene and erthe.
16 Ọ̀run àní ọ̀run ni ti Olúwa: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
Heuene of `heuene is to the Lord; but he yaf erthe to the sones of men.
17 Òkú kò lè yìn Olúwa, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
Lord, not deed men schulen herie thee; nether alle men that goen doun in to helle.
18 Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún Olúwa láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin Olúwa.
But we that lyuen, blessen the Lord; fro this tyme now and til in to the world.

< Psalms 115 >