< Psalms 112 >

1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run, tí ó ní inú dídùn ńlá sí àwọn òfin rẹ̀.
Alléluia! Heureux l'homme qui craint l'Éternel, et a un grand goût pour ses commandements!
2 Irú-ọmọ rẹ̀ yóò jẹ́ alágbára ní ayé: ìran àwọn olóòtítọ́ ni a ó bùkún fún.
Sa race sera puissante sur la terre, et la postérité du juste sera bénie.
3 Ọlá àti ọrọ̀ yóò wà nínú ilé rẹ̀; òdodo rẹ̀ sì dúró láé.
L'aisance et la richesse sont dans sa maison, et sa justice demeure éternellement.
4 Fún olóòótọ́ ni ìmọ́lẹ̀ yóò tàn fún ní òkùnkùn: olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú àti òdodo.
Dans les ténèbres la lumière se lève pour le juste; il est miséricordieux, clément et juste.
5 Ènìyàn rere fi ojúrere hàn, a sì wínni; ìmòye ni yóò máa fi la ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀.
Le bonheur est pour celui qui donne et qui prête, qui pour soutenir sa cause se fonde sur le droit.
6 Dájúdájú a kì yóò le yí ní ipò padà láéláé: olódodo ni a ó máa ṣe ìrántí rẹ láéláé.
Car il n'est jamais ébranlé, et l'homme de bien laisse une mémoire éternelle.
7 Òun kì yóò béèrè ìyìn búburú: ọkàn rẹ̀ ti dúró, ó ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa.
Il ne redoute point un message funeste; son cœur est ferme, il se confie dans l'Éternel;
8 Ó ti mú ọkàn rẹ̀ gbilẹ̀, ẹ̀rù kí yóò bà á, títí yóò fi rí ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá rẹ̀.
son cœur a de l'assurance, il est sans crainte, attendant que ses ennemis réjouissent ses regards.
9 Ó ti pín ká, ó ti fi fún àwọn olùpọ́njú, nítorí òdodo rẹ̀ dúró láé; ìwo rẹ̀ ní a ó gbé sókè pẹ̀lú ọlá.
Il distribue, il donne aux indigents; sa justice demeure éternellement; sa tête se lève avec gloire.
10 Ènìyàn búburú yóò ri, inú wọn yóò sì bàjẹ́, yóò sì pa eyín keke, yó sì yọ dànù: èròǹgbà ọkàn ènìyàn búburú ni yóò ṣègbé.
L'impie en est témoin et il s'en chagrine, il grince des dents et se consume; les souhaits de l'impie sont mis à néant.

< Psalms 112 >