< Psalms 111 >

1 Ẹ máa yin Olúwa. Èmi yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi, ní àwùjọ àwọn olóòtítọ́, àti ní ìjọ ènìyàn.
Louez l'Eternel. [Aleph] Je célébrerai l'Eternel de tout mon cœur, [Beth.] dans la compagnie des hommes droits, et dans l'assemblée.
2 Iṣẹ́ Olúwa tóbi, àwọn tí ó ní inú dídùn, ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀.
[Guimel.] Les œuvres de l'Eternel sont grandes, [Daleth.] Elles sont recherchées de tous ceux qui y prennent plaisir.
3 Iṣẹ́ rẹ̀ ni ọláńlá àti ògo: àti òdodo rẹ̀ dúró láéláé.
[He.] Son œuvre n'est que majesté et magnificence, [Vau.] et sa justice demeure à perpétuité.
4 Ó ti ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, láti máa rántí: Olúwa ni olóore-ọ̀fẹ́ àti pé ó kún fún àánú.
[Zaïn.] Il a rendu ses merveilles mémorables. [Heth.] L'Eternel est miséricordieux et pitoyable.
5 Ó ti fi oúnjẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀: òun ń rántí májẹ̀mú rẹ̀.
[Tet.] Il a donné à vivre à ceux qui le craignent; [Jod.] il s'est souvenu à toujours de son alliance.
6 Ó ti fihan àwọn ènìyàn rẹ̀ agbára iṣẹ́ rẹ̀ láti fún wọn ní ilẹ̀ ìlérí ní ìní.
[Caph.] Il a manifesté à son peuple la force de ses œuvres, [Lamed.] en leur donnant l'héritage des nations.
7 Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; gbogbo òfin rẹ̀ sì dájú.
[Mem.] Les œuvres de ses mains ne sont que vérité et équité; [Nun.] tous ses commandements sont véritables;
8 Wọ́n dúró láé àti láé, ní òtítọ́ àti òdodo ni a ṣe wọ́n.
[Samech.] Appuyés à perpétuité et à toujours, [Hajin.] étant faits avec fidélité et droiture.
9 Ó rán ìràpadà sí àwọn ènìyàn rẹ̀: ó pàṣẹ májẹ̀mú rẹ̀ títí láé, mímọ́ àti ọ̀wọ̀ ni orúkọ rẹ̀.
[Pe.] Il a envoyé la rédemption à son peuple; [Tsade.] il lui a donné une alliance éternelle; [Koph.] son nom est saint et terrible.
10 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọgbọ́n: òye dáradára ni yóò máa ṣe òfin rẹ̀, ìyìn rẹ̀ dúró láé.
[Resh.] Ce qu'il y a de capital dans la sagesse c'est la crainte de l'Eternel: [Scin.] tous ceux qui s'adonnent à faire ce qu'elle prescrit sont bien sages; [Thau.] sa louange demeure à perpétuité.

< Psalms 111 >