< Psalms 111 >
1 Ẹ máa yin Olúwa. Èmi yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi, ní àwùjọ àwọn olóòtítọ́, àti ní ìjọ ènìyàn.
Louez Yah! Je rendrai grâce à Yahvé de tout mon cœur, dans le conseil des hommes intègres et dans l'assemblée.
2 Iṣẹ́ Olúwa tóbi, àwọn tí ó ní inú dídùn, ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀.
Les œuvres de Yahvé sont grandes, réfléchis par tous ceux qui les apprécient.
3 Iṣẹ́ rẹ̀ ni ọláńlá àti ògo: àti òdodo rẹ̀ dúró láéláé.
Son œuvre est honneur et majesté. Sa justice est éternelle.
4 Ó ti ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, láti máa rántí: Olúwa ni olóore-ọ̀fẹ́ àti pé ó kún fún àánú.
Il a fait en sorte qu'on se souvienne de ses merveilles. Yahvé est gracieux et miséricordieux.
5 Ó ti fi oúnjẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀: òun ń rántí májẹ̀mú rẹ̀.
Il a donné de la nourriture à ceux qui le craignent. Il se souvient toujours de son engagement.
6 Ó ti fihan àwọn ènìyàn rẹ̀ agbára iṣẹ́ rẹ̀ láti fún wọn ní ilẹ̀ ìlérí ní ìní.
Il a montré à son peuple la puissance de ses œuvres, en leur donnant l'héritage des nations.
7 Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; gbogbo òfin rẹ̀ sì dájú.
Les œuvres de ses mains sont la vérité et la justice. Tous ses préceptes sont sûrs.
8 Wọ́n dúró láé àti láé, ní òtítọ́ àti òdodo ni a ṣe wọ́n.
Ils sont établis pour toujours et à jamais. Ils sont faits dans la vérité et la droiture.
9 Ó rán ìràpadà sí àwọn ènìyàn rẹ̀: ó pàṣẹ májẹ̀mú rẹ̀ títí láé, mímọ́ àti ọ̀wọ̀ ni orúkọ rẹ̀.
Il a envoyé la rédemption à son peuple. Il a établi son alliance pour toujours. Son nom est saint et impressionnant!
10 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọgbọ́n: òye dáradára ni yóò máa ṣe òfin rẹ̀, ìyìn rẹ̀ dúró láé.
La crainte de Yahvé est le commencement de la sagesse. Tous ceux qui font son travail ont une bonne compréhension. Sa louange est éternelle!