< Psalms 110 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Olúwa sọ fún Olúwa mi pé, “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi, títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”
Dávidé; zsoltár. Monda az Úr az én uramnak: Ülj az én jobbomon, a míg ellenségeidet zsámolyul vetem a te lábaid alá.
2 Olúwa yóò na ọ̀pá agbára rẹ̀ láti Sioni wá, ìwọ jẹ ọba láàrín àwọn ọ̀tá rẹ.
A te hatalmad pálczáját kinyújtja az Úr Sionból, mondván: Uralkodjál ellenségeid között!
3 Àwọn ènìyàn rẹ jẹ́ ọ̀rẹ́ àtinúwá ní ọjọ́ ìjáde ogun rẹ, nínú ẹwà mímọ́, láti inú òwúrọ̀ wá ìwọ ni ìrì ẹwà rẹ.
A te néped készséggel siet a te sereggyűjtésed napján, szentséges öltözetekben; hajnalpir méhéből leszen ifjaidnak harmatja.
4 Olúwa ti búra, kò sì í yí ọkàn padà pé, “Ìwọ ni àlùfáà, ní ipasẹ̀ Melkisedeki.”
Megesküdt az Úr és meg nem másítja: Pap vagy te örökké Melkhisedek rendje szerint.
5 Olúwa, ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni yóò lu àwọn ọba bolẹ̀ ni ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
Az Úr a te jobbod felől; megrontja az ő haragja napján a királyokat;
6 Yóò ṣe ìdájọ́ láàrín kèfèrí, yóò kún ibùgbé wọn pẹ̀lú òkú ara; yóò fọ́n àwọn olórí ká sí orí ilẹ̀ ayé tí ó gbòòrò.
Ítéletet tart a nemzetek között; telve lesz holttestekkel; összezúz messze földön minden főt.
7 Yóò mu nínú odò ṣíṣàn ní ọ̀nà: nítorí náà ni yóò ṣe gbé orí sókè.
Az út mellett való patakból iszik; ezért emeli fel az ő fejét.

< Psalms 110 >