< Psalms 110 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Olúwa sọ fún Olúwa mi pé, “Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi, títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ.”
Psaume de David. L'Éternel a dit à mon Seigneur: «Assieds-toi à ma droite, Jusqu'à ce que j'aie contraint tes ennemis A te servir de marchepied.»
2 Olúwa yóò na ọ̀pá agbára rẹ̀ láti Sioni wá, ìwọ jẹ ọba láàrín àwọn ọ̀tá rẹ.
L'Éternel étendra loin de Sion le sceptre de ta puissance: Tu exerceras ta domination sur tes ennemis!
3 Àwọn ènìyàn rẹ jẹ́ ọ̀rẹ́ àtinúwá ní ọjọ́ ìjáde ogun rẹ, nínú ẹwà mímọ́, láti inú òwúrọ̀ wá ìwọ ni ìrì ẹwà rẹ.
Ton peuple accourt plein d'ardeur, Le jour où tu rassembles ton armée. Revêtue d'ornements sacrés, Ta jeune milice vient à toi Comme une rosée qui naît du sein de l'aurore.
4 Olúwa ti búra, kò sì í yí ọkàn padà pé, “Ìwọ ni àlùfáà, ní ipasẹ̀ Melkisedeki.”
L'Éternel en a fait le serment, et il ne s'en repentira point: «Tu es sacrificateur pour toujours, A la façon de Melchisédec.»
5 Olúwa, ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni yóò lu àwọn ọba bolẹ̀ ni ọjọ́ ìbínú rẹ̀.
Le Seigneur est à ta droite; Il écrasera les rois au jour de sa colère.
6 Yóò ṣe ìdájọ́ láàrín kèfèrí, yóò kún ibùgbé wọn pẹ̀lú òkú ara; yóò fọ́n àwọn olórí ká sí orí ilẹ̀ ayé tí ó gbòòrò.
Il jugera les nations; tout sera plein de cadavres. Il écrasera le chef qui domine sur un vaste pays.
7 Yóò mu nínú odò ṣíṣàn ní ọ̀nà: nítorí náà ni yóò ṣe gbé orí sókè.
Il boira, sur la route, de l'eau du torrent; Puis il marchera la tête haute.

< Psalms 110 >