< Psalms 11 >
1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa. Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé, “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
Mai marelui muzician, un psalm al lui David. În DOMNUL îmi pun încrederea; cum spuneți voi sufletului meu: Fugi ca o pasăre la muntele vostru?
2 Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀; wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn láti tafà níbi òjìji sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
Căci, iată, cei stricați își încordează arcul, își pregătesc săgeata pe coardă, ca să poată trage în ascuns spre cei integri în inimă.
3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́ kí ni olódodo yóò ṣe?”
Dacă temeliile sunt distruse, ce poate face cel drept?
4 Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn; ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
DOMNUL este în templul său sfânt, tronul DOMNULUI este în cer; ochii lui privesc, pleoapele lui încearcă pe copiii oamenilor.
5 Olúwa ń yẹ olódodo wò, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
DOMNUL încearcă pe cel drept, dar pe cel stricat și pe cel ce iubește violența, sufletul lui îi urăște.
6 Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó; àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
Peste cei stricați el va ploua cu capcane, foc și pucioasă și o groaznică furtună, aceasta va fi partea paharului lor.
7 Nítorí, olódodo ní Olúwa, o fẹ́ràn òdodo; ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.
Căci DOMNUL cel drept iubește dreptatea, înfățișarea lui privește pe cei integri.