< Psalms 11 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa. Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé, “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
Przewodnikowi chóru. Psalm Dawida. W PANU pokładam ufność. Jakże więc możecie mówić mojej duszy: Odleć [jak] ptak na twoją górę?
2 Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀; wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn láti tafà níbi òjìji sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
Bo oto niegodziwi napinają łuk, kładą strzałę na cięciwę, aby w ciemności strzelać do tych, którzy są prawego serca.
3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́ kí ni olódodo yóò ṣe?”
Gdy zostaną zburzone fundamenty, cóż może zrobić sprawiedliwy?
4 Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn; ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
PAN [jest] w swym świętym przybytku, tron PANA [jest] w niebie, jego oczy patrzą, jego powieki badają synów ludzkich.
5 Olúwa ń yẹ olódodo wò, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
PAN doświadcza sprawiedliwego, ale jego dusza nienawidzi niegodziwego i tego, kto kocha bezprawie.
6 Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó; àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
Spuści na niegodziwych deszcz sideł, ognia i siarki, a [palący] wicher będzie udziałem ich kielicha.
7 Nítorí, olódodo ní Olúwa, o fẹ́ràn òdodo; ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.
Bo sprawiedliwy PAN kocha sprawiedliwość, jego oczy patrzą na prawego.

< Psalms 11 >