< Psalms 11 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa. Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé, “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
Au maître-chantre. — De David. J'ai cherché mon refuge en l'Éternel. Comment dites-vous à mon âme: «Fuis vers tes montagnes, comme l'oiseau!
2 Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀; wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn láti tafà níbi òjìji sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
Car voici que les méchants bandent l'arc; Ils ont ajusté leur flèche sur la corde, Pour tirer, dans l'ombre, sur ceux qui ont le coeur droit.
3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́ kí ni olódodo yóò ṣe?”
Quand les fondements sont renversés, Le juste, que fera-t-il?»
4 Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn; ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
L'Éternel est dans sa demeure sainte: L'Éternel a son trône dans les cieux. Ses yeux observent; Ses regards sondent les fils des hommes.
5 Olúwa ń yẹ olódodo wò, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
L'Éternel sonde le juste; Mais il hait le méchant et celui qui se plaît à la violence.
6 Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó; àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
Il fera pleuvoir sur les méchants Des charbons ardents, du feu et du soufre. Un vent brûlant, tel est le sort qu'ils auront en partage!
7 Nítorí, olódodo ní Olúwa, o fẹ́ràn òdodo; ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.
Oui, l'Éternel est juste; il aime la justice. Les hommes droits contempleront sa face.

< Psalms 11 >