< Psalms 11 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa. Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé, “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
Pour le musicien en chef. Par David. En Yahvé, je me réfugie. Comment peux-tu dire à mon âme: « Fuis comme un oiseau vers ta montagne »?
2 Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀; wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn láti tafà níbi òjìji sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
Car voici, les méchants bandent leurs arcs. Ils ont placé leurs flèches sur les cordes, pour qu'ils puissent tirer dans l'obscurité sur ceux qui ont le cœur droit.
3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́ kí ni olódodo yóò ṣe?”
Si les fondations sont détruites, que peut faire le juste?
4 Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn; ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
Yahvé est dans son temple saint. Yahvé est sur son trône dans le ciel. Ses yeux observent. Ses yeux examinent les enfants des hommes.
5 Olúwa ń yẹ olódodo wò, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
Yahvé examine les justes, mais son âme déteste le méchant et celui qui aime la violence.
6 Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó; àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
Sur les méchants, il fait pleuvoir des charbons ardents; le feu, le soufre et le vent brûlant seront la part de leur coupe.
7 Nítorí, olódodo ní Olúwa, o fẹ́ràn òdodo; ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.
Car Yahvé est juste. Il aime la droiture. Les hommes droits verront sa face.

< Psalms 11 >