< Psalms 11 >
1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa. Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé, “Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.
Til Sangmesteren; af David. Jeg haaber paa Herren; hvorledes kunne I da sige til min Sjæl: Fly til eders Bjerg som en Fugl?
2 Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀; wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn láti tafà níbi òjìji sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.
Thi se, de ugudelige spænde Buen, de berede deres Pil paa Strengen, at skyde i Mørke paa de oprigtige af Hjertet.
3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́ kí ni olódodo yóò ṣe?”
Thi Grundvoldene nedbrydes; hvad kunde en retfærdig udrette?
4 Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀; Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run. Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn; ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.
Herren er i sit hellige Tempel, Herrens Trone er i Himmelen; hans Øjne se, hans Øjenlaage prøve Menneskens Børn.
5 Olúwa ń yẹ olódodo wò, ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.
Herren prøver en retfærdig; men den ugudelige og den, som elsker Vold, dem hader hans Sjæl.
6 Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó; àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.
Han skal lade regne Snarer over de ugudelige; Ild og Svovl og et vældigt Stormvejr skal blive deres Bægers Del.
7 Nítorí, olódodo ní Olúwa, o fẹ́ràn òdodo; ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.
Thi Herren er retfærdig, elsker Retfærdighed; hans Ansigt skuer en oprigtig.