< Psalms 109 >
1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
Nǝƣmiqilǝrning bexiƣa tapxurulup oⱪulsun dǝp, Dawut yazƣan küy: — I mǝdⱨiyǝmning Igisi Hudayim, jim turma!
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
Mana rǝzillǝrning aƣzi, mǝkkarlarning aƣzi kɵz aldimda yoƣan eqildi; Ular yalƣanqi til bilǝn manga ⱪarxi sɵzlidi.
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
Nǝprǝtlik sɵzlǝr bilǝn meni qulƣap, Ular bikardin-bikar manga zǝrbǝ bǝrmǝktǝ.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Muⱨǝbbitim üqün ular manga ⱪarxi xikayǝtqi boldi, Mǝn bolsam — duaƣa berildim.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
Yahxiliⱪim üqün yamanliⱪ, Sɵygüm üqün nǝprǝt ⱪayturdi.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Ⱨǝrbirining üstidǝ rǝzil bir adǝm tǝyinligǝysǝn, Uning ong yenida bir dǝwagǝr tursun.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
U soraⱪ ⱪilinƣanda ǝyibdar bolup qiⱪsun, Duasi gunaⱨ dǝp ⱨesablansun.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
Künliri ⱪisⱪa bolsun, Mǝnsipini baxⱪisi igilisun.
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Baliliri yetim ⱪalsun, Hotuni tul bolsun.
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
Oƣulliri sǝrgǝrdan tilǝmqi bolsun, Turƣan harabilikliridin nan izdǝp.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Jazanihor uning igiliki üstigǝ tor taxlisun, Meⱨnǝt ǝjrini yatlar bulap-talisun.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Uningƣa meⱨribanliⱪ kɵrsitidiƣan birsi bolmisun, Yetim ⱪalƣan baliliriƣa iltipat ⱪilƣuqi bolmisun.
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Uning nǝsli ⱪurutulsun; Kelǝr ǝwladida namliri ɵqürülsun.
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Ata-bowilirining ⱪǝbiⱨlikining ǝyibliri Pǝrwǝrdigarning yadida ⱪalsun, Anisining gunaⱨi ɵqürülmisun.
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Bularning ǝyibliri daim Pǝrwǝrdigarning kɵz aldida bolsun, Xuning bilǝn U ularning nam-ǝmilini yǝr yüzidin ɵqürüp taxlaydu.
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
Qünki [rǝzil kixi] meⱨribanliⱪ kɵrsitixni ⱨeq esigǝ kǝltürmidi, Bǝlki ezilgǝn, yoⱪsul ⱨǝm dili sunuⱪlarni ɵltürmǝkkǝ ⱪoƣlap kǝldi.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
U lǝnǝt oⱪuxⱪa amraⱪ idi, Xunga lǝnǝt uning bexiƣa kelidu; Bǝht tilǝxkǝ rayi yoⱪ idi, Xunga bǝht uningdin yiraⱪ bolidu.
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
U lǝnǝtlǝrni ɵzigǝ kiyim ⱪilip kiygǝn; Xunga bular aⱪⱪan sudǝk uning iq-baƣriƣa, Maydǝk, sɵngǝklirigǝ kiridu;
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Bular uningƣa yepinƣan tonidǝk, Ⱨǝrdaim baƣlanƣan bǝlweƣidǝk qaplansun.
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
Bular bolsa meni ǝyibligüqilǝrgǝ Pǝrwǝrdigarning bekitkǝn mukapati bolsun! Mening yaman gepimni ⱪilƣanlarning in’ami bolsun!
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
Biraⱪ Sǝn, Pǝrwǝrdigar Rǝbbim, Ɵz naming üqün mening tǝripimdǝ bir ix ⱪilƣaysǝn, Meⱨir-muⱨǝbbiting ǝla bolƣaqⱪa, Meni ⱪutⱪuzƣaysǝn;
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Qünki mǝn ezilgǝn ⱨǝm ⱨajǝtmǝndurmǝn, Ⱪǝlbim hǝstǝ boldi.
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
Mǝn ⱪuyax uzartⱪan kɵlǝnggidǝk yoⱪilay dǝp ⱪaldim, Qekǝtkǝ ⱪeⱪiwetilgǝndǝk qǝtkǝ ⱪeⱪiwetildim.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
Roza tutⱪinimdin tizlirim ketidu, Ətlirim sizip ketidu.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
Xunglaxⱪa mǝn ular aldida rǝswa boldum; Ular manga ⱪaraxⱪanda, bexini silkixmǝktǝ.
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Manga yardǝmlǝxkǝysǝn, i Pǝrwǝrdigar Hudayim, Ɵzgǝrmǝs muⱨǝbbiting boyiqǝ meni ⱪutⱪuzƣaysǝn;
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
Xuning bilǝn ular buning Sening ⱪolungdiki ix ikǝnlikini, Buni ⱪilƣuqining Sǝn Pǝrwǝrdigar ikǝnlikini bilsun.
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
Ular lǝnǝt oⱪuwǝrsun, Sǝn bǝht ata ⱪilƣaysǝn; Ular ⱨujum ⱪilixⱪa turƣanda, hijalǝttǝ ⱪalsun, Biraⱪ ⱪulung xadlansun!
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Meni ǝyibligüqilǝr hijalǝt bilǝn kiyinsun, Ular ɵz xǝrmǝndilikini ɵzlirigǝ ton ⱪilip yepinsun.
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
Aƣzimda Pǝrwǝrdigarƣa zor tǝxǝkkür-mǝdⱨiyǝ ⱪaytürimǝn; Bǝrⱨǝⱪ, kɵpqilik arisida turup Uni mǝdⱨiyilǝymǝn;
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
Qünki ⱨajǝtmǝnning jenini gunaⱨⱪa bekitmǝkqi bolƣanlardin ⱪutⱪuzux üqün, [Pǝrwǝrdigar] uning ong yenida turidu.