< Psalms 109 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
Przewodnikowi chóru. Psalm Dawida. Boże mojej chwały, nie milcz;
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
Bo otworzyły się przeciwko mnie usta niegodziwego i usta podstępnego; mówili przeciwko mnie językiem kłamliwym;
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
Otoczyli mnie słowami nienawiści i walczą przeciwko mnie bez przyczyny.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Sprzeciwiają mi się w zamian za moją miłość, choć ja się [za nich] modliłem.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
Odpłacają mi złem za dobro i nienawiścią za moją miłość.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Postaw nad nim niegodziwego, a szatan niech stoi po jego prawicy.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
Gdy stanie przed sądem, niech wyjdzie potępiony, a jego modlitwa niech zamieni się w grzech.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
Niech jego dni będą krótkie, a jego urząd niech przejmie inny.
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Niech jego dzieci będą sierotami, a jego żona wdową.
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
Niech jego dzieci będą tułaczami i żebrzą, niech żebrzą [z dala] od swoich opustoszałych miejsc.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Niech lichwiarz przejmie wszystko, co ma, a obcy niech rozgrabią [owoc] jego pracy.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Niech nie będzie nikogo, kto by mu okazał miłosierdzie; niech nie będzie nikogo, kto by się zlitował nad jego sierotami.
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Niech jego potomkowie zostaną wykorzenieni, niech ich imię zginie w drugim pokoleniu.
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Niech PAN pamięta nieprawość jego przodków, a grzech jego matki niech nie będzie zgładzony.
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Niech będą zawsze przed PANEM, aż wykorzeni z ziemi pamięć o nich;
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
Dlatego że nie pamiętał, by okazać miłosierdzie, ale prześladował człowieka nędznego i ubogiego, a strapionego w sercu chciał zabić.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
Skoro umiłował przekleństwo, niech na niego spadnie; [skoro] nie chciał błogosławieństwa, niech się od niego oddali.
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
Ubierał się w przekleństwo jak w szatę, więc niech wejdzie jak woda do jego wnętrzności i jak oliwa do jego kości.
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Niech mu będzie jak płaszcz, który go okrywa, i jak pas, który go zawsze opasuje.
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
Taka niech będzie zapłata od PANA dla moich przeciwników i tych, którzy źle mówią przeciwko mojej duszy.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
Ale ty, BOŻE, Panie, ujmij się za mną przez wzgląd na twoje imię; ocal mnie, bo wielkie jest twoje miłosierdzie.
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
[Jestem] bowiem ubogi i nędzny, a moje serce we mnie jest zranione.
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
Niknę jak cień, który się chyli, strząsają mnie jak szarańczę.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
Moje kolana słabną od postu, a moje ciało wychudło bez tłuszczu.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
Stałem się też dla nich pośmiewiskiem; [gdy] mnie widzą, kiwają głowami.
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Wspomóż mnie, PANIE, mój Boże; wybaw mnie według swego miłosierdzia;
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
Aby mogli poznać, że to twoja ręka; że ty, PANIE, to uczyniłeś.
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
Niech oni przeklinają, ale ty błogosław; [gdy] powstają, niech będą zawstydzeni, a twój sługa niech się weseli.
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Niech moi przeciwnicy okryją się hańbą i niech się okryją własnym wstydem jak płaszczem.
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
Będę wielce wysławiał PANA swymi ustami i pośród tłumu będę go chwalić;
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
Bo staje po prawicy nędznego, aby go wybawić od tych, którzy osądzają jego duszę.

< Psalms 109 >