< Psalms 109 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
Przedniejszemu śpiewakowi psalm Dawidowy. O Boże chwały mojej! nie milcz;
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
Bo się usta niepobożnego, i usta kłamliwe przeciwko mnie otworzyły; mówili przeciwko mnie językiem kłamliwym,
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
A słowy jadowitemi ogarnęli mię, walcząc przeciwko mnie bez wszekiej przyczyny.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Przeciwili mi się za miłość moję, chociażem się za nich modlił.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
Oddawają mi złem za dobre; a nienawiścią za miłość moję.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Postawże nad nim bezbożnika, a przeciwnik niech stoi po prawej ręce jego.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
Gdy przed sądem stanie, niech wynijdzie potępionym, a modlitwa jego niech się w grzech obróci.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
Niech będą dni jego krótkie, a przełożeństwo jego niech inny weźmie.
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Niech dzieci jego będą sierotami, a żona jego wdową.
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
Niech będą biegunami i tułaczami synowie jego, niech żebrzą, a niech żebrzą wychodząc z pustek swoich.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Niech lichwiarz załapi wszystko, co jest jego, a niech obcy rozchwycą pracę jego.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Niech nie będzie ktoby mu miłosierdzie pokazał, niech nie będzie, ktoby się zmiłował nad sierotami jego.
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Potomkowie jego niech z korzenia wycięci będą; w drugiem pokoleniu niech będzie wygładzone imię ich.
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Niech przyjdzie na pamięć nieprawość przodków jego przed Panem, a grzech matki jego niechaj nie będzie zgładzony.
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Niech będą przed Panem ustawicznie, ażby wygładził z ziemi pamiątkę ich,
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
Przeto, że nie pamiętał, aby czynił miłosierdzie, ale prześladował człowieka nędznego i ubogiego, a tego, który był serca utrapionego, chciał zamordować.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
Ponieważ umiłował przeklęstwo, niechże przyjdzie na niego; niechciał błogosławieństwa niechże będzie oddalone od niego.
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
A tak niech będzie obleczony w przeklęstwo, jako w szatę swoję; a niech wnijdzie jako woda we wnętrzności jego, a jako olej w kości jego.
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Niech mu to będzie jako płaszcz do przodziania, a jako pas dla ustawicznego opasywania.
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
Takowa zapłata niech będzie przeciwnikom moim od Pana, i tym, którzy źle mówią przeciwko duszy mojej.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
Ale ty, Panie! o Panie! użyj nademną litości dla imienia twego; a iż dobre jest miłosierdzie twoje, wyrwijże mię.
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Bomci ja jest ubogi i nędzny, a serce moje zranione jest w wnętrznościach moich.
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
Jako cień, który ustępuje, uchodzić muszę; zganiają mię jako szarańczę.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
Kolana moje upadają od postu, a ciało moje wychudło z tłustości.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
Nadto stałem się im pośmiewiskiem; gdy mię widzą, kiwają głowami swemi.
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Wspomóżże mię, o Panie, Boże mój! zachowaj mię według miłosierdzia swego,
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
Tak, aby poznać mogli, iż to ręka twoja, a żeś ty, Panie! to uczynił.
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
Niechże oni przeklinają, ty błogosław; którzy powstali, niech będą zawstydzeni, aby się weselił sługa twój.
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Niech będą przeciwnicy moi w hańbę obleczeni, a niech się przyodzieją, jako płaszczem, zelżywością swoją.
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
Będę Pana wielce wysławiał usty swemi, a w pośród wielu chwalić go będę.
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
Przeto, że stoi po prawej stronie nędznemu, aby go wybawił od tych, którzy osądzają duszę jego.

< Psalms 109 >