< Psalms 109 >
1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
Dāvida dziesma, dziedātāju vadonim. Ak Dievs, ko es slavēju, nestāv klusu!
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
Jo bezdievīgu muti un viltīgu muti tie pret mani ir atvēruši, tie runā uz mani ar melu mēli.
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
Ar naidīgiem vārdiem tie metās ap mani un karo pret mani bez vainas.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Par to, ka es tos mīlēju, tie turas man pretī; bet es lūdzu Dievu.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
Tie man maksā ļaunu par labu un ienaidību par mīlestību.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Cel pār to vienu bezdievi, un viens pretinieks lai viņam stāv pa labo roku.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
Kad viņš top tiesāts, tad lai top pazudināts, un viņa Dieva lūgšana lai viņam top par grēku.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
Lai viņa dienas iet mazumā, un viņa amatu cits lai dabū.
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Viņa bērni lai paliek par bāriņiem un viņa sieva par atraitni.
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
Lai viņa bērni skraida apkārt un ubago un maizes meklē tālu no savām izpostītām māju vietām.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Lai tas parādu dzinējs izplēš visu, kas tam pieder, un sveši lai aplaupa viņa peļņu.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Lai tam nav, kas parāda žēlastību, un lai nav, kas žēlo viņa bāriņus.
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Lai viņa pēcnākamie top izdeldēti; viņu vārds lai izzūd otrā augumā.
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Viņa tēvu noziegums lai top pieminēts Tā Kunga priekšā, un viņa mātes grēki lai neizzūd.
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Lai tie vienmēr paliek Tā Kunga priekšā, un viņa piemiņa lai no zemes top izdeldēta.
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
Tādēļ ka viņš nebūt nepieminēja žēlastību darīt, bet vajāja bēdīgo un nabagu un to, kam bija noskumusi sirds, ka viņš to nokautu.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
Tāpēc ka viņš lāstu gribēja, tas viņam nāks; un svētības viņam negribējās, tad tā arī paliks tālu no viņa.
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
Un viņš aptērpās ar lāstu, tā kā ar drēbēm, un tas nāca viņa iekšās kā ūdens un kā eļļa viņa kaulos.
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Tad lai tas viņam ir kā apģērbs, ar ko tas apsedzās, un josta, ar ko tas allaž apjožas.
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
Šī alga lai notiek no Tā Kunga maniem pretiniekiem un tiem, kas ļaunu runā pret manu dvēseli.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
Bet Tu, ak Kungs, dari ar mani Sava vārda pēc, jo Tava žēlastība ir laba; izglāb mani.
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Jo es esmu bēdīgs un nabags, un mana sirds iekš manis ir ievainota.
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
Es aizeju kā ēna pavakarē, un topu vajāts kā sisenis.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
Mani ceļi šļūk no gavēšanas, un mana miesa izdilusi, ka treknuma vairs nav.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
Un es tiem esmu par apsmieklu; kad tie mani redz, tad tie krata galvu.
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Palīdz man, Kungs, mans Dievs, atpestī mani pēc Savas žēlastības!
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
Tad tie atzīs, ka tā Tava roka, ka Tu, Kungs, to darījis.
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
Kad tie lād, tad Tu svētī; kad tie ceļas, tad lai top kaunā; bet Tavs kalps lai priecājās.
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Mani pretinieki lai ar kaunu top apģērbti un ar savu negodu apsegti kā ar svārkiem.
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
Es Tam Kungam no sirds pateikšu ar savu muti un Tam dziedāšu lielā draudzē.
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
Jo tam bēdīgam Viņš stāv pa labo roku, to atpestīdams no tiem, kas viņa dvēseli notiesā.