< Psalms 109 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
[Psalm lal David] Nga kaksakin kom, O God; nikmet mutana misla!
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
Mwet koluk ac mwet kikiap elos lainyu. Elos fahk kas kikiap keik,
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
Ac elos fahk kas koluk keik — Elos lainyu ke wangin sripa.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Nga ne lungse elos ac pre kaclos A elos nu srungayu na.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
Elos folokin orekma wo luk ke orekma koluk, Ac srungayu ke nga lungse elos.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Sulela sie mwet nununku sesuwos in nununku mwet lokoalok luk, Ac lela sie mwet su srungal in tafwel.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
Lela in nununkeyuk el ac koneyukyak tuh na oasr mwatal. Lela God Elan akilen lah kas in pre lal uh oana sie ma koluk.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
Lela tuh in fototo moul lal; Ac lela siena mwet in eis acn sel!
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Lela tuh tulik natul in mukaimtal, Ac mutan kial in katinmas!
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
Lela tulik natul in mwet takusrkusr ac mwet ngusr; Lela tuh elos in lillilyak liki mahnum in lohm elos muta loac.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Lela tuh mwet el orek soemoul yoro in eisla ma lal nukewa, Ac lela tuh mwetsac in eis woiyen orekma lal.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Lela in wangin mwet sifilpa kulang nu sel Ac in wangin pac mwet lohang nu sin tulik mukaimtal natul uh.
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Lela tuh fwil natul nukewa in misa, Ac in mulkinyukla inel ke fwil se tokol.
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Lela tuh LEUM GOD Elan esam na ma koluk lun papa tumal Ac tia nunak munas nu ke ma koluk lun nina kial.
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Lela tuh LEUM GOD Elan esam ma koluk lalos pacl e nukewa, A elos sifacna in iyuklana ac tiana sifil esamyuk!
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
Mweyen mwet se ingan el tiana nunkauk elan moul in kulang; El akkeokye ac uniya mwet sukasrup, Mwet enenu, ac mwet munas.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
El lungse selngawi mwet — lela in selngawiyuk el! El srunga in akinsewowoye mwet — lela in wangin mwet akinsewowoyal!
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
El oru selnga uh fisrasr oana nuknukyang uh; Lela manol in toki ac arulana sroksroki ke selnga lal, Ac in tilyang nu in sri kacl oana mwe akmusra.
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Lela selnga lal uh in nokmulla oana nuknuk Ac in losilya oana sie mwe lohl.
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
LEUM GOD, kalyei mwet lokoalok luk in lumah ingan — Elos su fahk kas koluk lainyu.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
Tusruktu, O LEUM GOD Fulat luk, kasreyu oana ke kom wulela, Ac moliyula ke wolana lun lungse lom.
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Tuh nga mwet sukasrup ac enenu; Mwe keok luk arulana fakisya insiuk,
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
Ac nga apkuran in wanginla, oana lullul in eku — Ukukla nga, oana sie won srisrik.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
Intik munasla ke wanginla loalok, Ac nga sri na kolo.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
Ke mwet elos liyeyu, elos isrunyu; Elos niwurwur sik ac usruk sifalos.
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
O LEUM GOD luk, kasreyu; Moliyula ke lungse pwaye lom.
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
Oru tuh mwet lokoalok luk in etu Lah kom pa moliyula uh.
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
Sahp elos ac selngawiyu, tusruktu kom fah akinsewowoyeyu. Lela tuh elos su akkeokyeyu in kutangyukla, Ac lela tuh nga, su mwet kulansap lom, in engan.
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Lela mwet lokoalok luk in nukla ke mwekin; Lela elos in nokomang mwekin lalos oana sie nuknuk.
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
Nga fah sang kulo nu sin LEUM GOD ke pusra lulap; Nga fah kaksakunul in walil uh,
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
Mweyen El kasru el su sukasrup, Ac molella liki poun mwet su kena eisalang nu ke misa.

< Psalms 109 >