< Psalms 109 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
Az éneklőmesternek, Dávidé; zsoltár. Én dicséretemnek Istene, ne hallgass!
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
Mert a gonosznak szája és az álnokságnak szája felnyilt ellenem, hazug nyelvvel beszélnek én velem.
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
És körülvesznek engem gyűlölséges beszédekkel, és ostromolnak engem ok nélkül.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Szeretetemért ellenkeznek velem, én pedig imádkozom.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
Roszszal fizetnek nékem a jóért, és gyűlölséggel az én szeretetemért.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Állíts fölibe gonoszt, és vádló álljon az ő jobb keze felől.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
Mikor törvénykezik, mint gonosz jőjjön ki; még az imádsága is bűnné legyen.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
Életének napjai kevesek legyenek, és a hivatalát más foglalja el.
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Fiai legyenek árvákká, a felesége pedig özvegygyé.
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
És bujdossanak az ő fiai és kolduljanak, és elpusztult helyeiktől távol keressenek eledelt.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Foglalja le minden jószágát az uzsorás, és idegenek ragadozzák el szerzeményét.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Ne legyen néki, a ki kegyelmet mutasson iránta, és ne legyen, a ki könyörüljön az ő árváin!
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Veszszen ki az ő maradéka; a második nemzedékben töröltessék el a nevök!
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Atyáinak álnoksága emlékezetben legyen az Úr előtt, és anyjának bűne el ne töröltessék!
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Mindenkor az Úr előtt legyenek, és emlékezetök is veszszen ki e földről,
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
A miatt, hogy nem gondolt arra, hogy kegyelmet gyakoroljon és üldözte a szegény és nyomorult embert, és a megkeseredett szívűt, hogy megölje.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
Mivelhogy szerette az átkot, azért érte el őt; és mivel nem volt kedve az áldáshoz, azért távozék az el ő tőle.
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
Úgy öltözte fel az átkot, mint a ruháját, azért ment beléje, mint a víz, és az ő csontjaiba, mint az olaj.
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Legyen az néki palástul, a melybe beburkolódzik, és övül, a melylyel mindenkor övezze magát.
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
Ez legyen jutalmok az Úrtól az én vádolóimnak, és a kik rosszat beszélnek az én lelkemre.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
De te, én Uram, Istenem, bánj velem a te nevedért; mivelhogy jó a te kegyelmed, szabadíts meg engem!
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Mert szegény és nyomorult vagyok én, még a szívem is megsebesíttetett én bennem.
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
Úgy hanyatlom el, mint az árnyék az ő megnyúlásakor; ide s tova hányattatom, mint a sáska.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
Térdeim tántorognak az éhségtől, és testem megfogyatkozott a kövérségtől.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
Sőt gyalázatossá lettem előttök; ha látnak engem, fejöket csóválják.
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Segíts meg engem, Uram Isten; szabadíts meg engem a te kegyelmed szerint!
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
Hadd tudják meg, hogy a te kezed munkája ez, hogy te cselekedted ezt, Uram!
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
Átkozzanak ők, de te áldj meg! Feltámadnak, de szégyenüljenek meg és örvendezzen a te szolgád.
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Öltözzenek az én vádlóim gyalázatba, és burkolózzanak szégyenökbe, mint egy köpenybe!
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
Hálát adok az Úrnak felettébb az én számmal, és dicsérem őt a sokaság közepette!
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
Mert jobb keze felől áll a szegénynek, hogy megszabadítsa azoktól, a kik elítélik annak lelkét.

< Psalms 109 >