< Psalms 109 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
Veisuunjohtajalle; Daavidin virsi. Jumala, minun ylistykseni, älä ole vaiti.
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
Sillä he ovat avanneet minua vastaan jumalattoman ja petollisen suun, he puhuttelevat minua valheen kielellä.
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
Vihan sanoilla he ovat minut piirittäneet, ja syyttä he sotivat minua vastaan.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Rakkauteni palkaksi he minua vainoavat, mutta minä ainoastaan rukoilen.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
He kostavat minulle hyvän pahalla ja rakkauteni vihalla.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Aseta jumalaton mies häntä vastaan, ja seisokoon syyttäjä hänen oikealla puolellansa.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
Oikeuden edessä hän joutukoon syyhyn, ja hänen rukouksensa tulkoon synniksi.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
Hänen päivänsä olkoot harvat, ottakoon toinen hänen kaitsijatoimensa.
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Tulkoot hänen lapsensa orvoiksi ja hänen vaimonsa leskeksi.
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
Kierrelkööt hänen lapsensa alati kerjäten, anelkoot kaukana kotinsa raunioilta.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Anastakoon koronkiskuri kaiken hänen omansa, ja riistäkööt vieraat hänen vaivannäkönsä.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Älköön kukaan osoittako hänelle laupeutta, älköönkä kukaan armahtako hänen orpojansa.
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Hänen jälkeläisensä hävitkööt sukupuuttoon, pyyhittäköön heidän nimensä pois toisessa polvessa.
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Hänen isiensä rikkomukset pysykööt Herran muistossa, älköönkä hänen äitinsä syntiä pyyhittäkö pois.
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Olkoot ne Herran edessä alati, ja hävittäköön hän heidän muistonsa maan päältä.
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
Sillä se mies ei ajatellutkaan tehdä laupeutta, vaan vainosi kurjaa ja köyhää ja sydämen tuskassa olevaa, tappaaksensa hänet.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
Hän rakasti kirousta, ja se kohtasi häntä; hän ei huolinut siunauksesta, ja se väistyi hänestä kauas.
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
Hän puki kirouksen yllensä niinkuin vaatteensa, ja se meni hänen sisuksiinsa niinkuin vesi ja hänen luihinsa niinkuin öljy.
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Se olkoon hänellä viittana, johon hän verhoutuu, ja vyönä, johon hän aina vyöttäytyy.
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
Tämä olkoon Herralta minun vainoojaini palkka ja niiden, jotka puhuvat pahaa minua vastaan.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
Mutta sinä, Herra, Herra, auta minua nimesi tähden, sillä sinun armosi on hyvä, pelasta minut.
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Sillä minä olen kurja ja köyhä, ja sydämeni on haavoitettu minun rinnassani.
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
Minä katoan pois kuin pitenevä varjo, minut pudistetaan pois kuin heinäsirkka.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
Polveni horjuvat paastoamisesta, ja minun ruumiini on laihtunut lihattomaksi.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
Ja minä olen joutunut heidän herjattavakseen, minut nähdessään he nyökyttävät päätänsä.
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Auta minua, Herra, minun Jumalani, pelasta minut armosi jälkeen;
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
ja he saakoot tuta, että tämä on sinun kätesi, että sinä, Herra, sen teit.
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
Jos he kiroavat, siunaa sinä, jos he nousevat, joutukoot häpeään, mutta palvelijasi saakoon iloita.
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Olkoon häväistys minun vainoojaini pukuna, ja verhotkoon heitä heidän häpeänsä niinkuin viitta.
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
Minä suullani kiitän suuresti Herraa, ja monien keskellä minä ylistän häntä.
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
Sillä hän seisoo köyhän oikealla puolella pelastaakseen hänet niistä, jotka hänet tuomitsevat.

< Psalms 109 >