< Psalms 109 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Ọlọ́run, ti èmi ń fi ìyìn fún, má ṣe dákẹ́,
Davidin Psalmi, edelläveisaajalle. Jumala, minun kiitokseni, älä vaikene.
2 nítorí àwọn ènìyàn búburú àti ẹlẹ́tàn ti ya ẹnu wọn sí mi wọ́n ti fi ahọ́n èké sọ̀rọ̀ sí mi.
Sillä he ovat jumalattoman ja pettäväisen suunsa avanneet minua vastaan: he puhuvat minun kanssani viekkaalla kielellä,
3 Wọ́n fi ọ̀rọ̀ ìríra yí mi káàkiri; wọ́n bá mi jà láìnídìí
Ja myrkyllisillä sanoilla ovat he minun piirittäneet, ja sotivat minua vastaan ilman syytä.
4 Nípò ìfẹ́ mi, wọn ń ṣe ọ̀tá mi, ṣùgbọ́n èmi ń gba àdúrà.
Että minä heitä rakastan, ovat he minua vastaan; mutta minä rukoilen.
5 Wọ́n sì fi ibi san ìre fún mi àti ìríra fún ìfẹ́ mi.
He osoittavat minulle pahaa hyvän edestä ja vihaa rakkauden edestä.
6 Yan àwọn ènìyàn búburú láti dojúkọ jẹ́ kí àwọn olùfisùn dúró ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.
Aseta jumalattomat hänen päällensä, ja perkele seisokaan hänen oikialla kädellänsä.
7 Kí a dá a lẹ́bi nígbà tí a bá ṣe ìdájọ́ kí àdúrà rẹ̀ kí ó lè di ìkọ̀sílẹ̀.
Koska hän tuomitaan, niin lähtekään siitä ulos jumalattomana, ja hänen rukouksensa olkoon synti.
8 Kí ọjọ́ rẹ̀ kí ó kúrú; kí ẹlòmíràn kí ó rọ́pò iṣẹ́ rẹ̀.
Olkoon hänen päivänsä harvat, ja hänen virkansa ottakoon toinen.
9 Kí àwọn ọmọ rẹ̀ di aláìní baba kí aya rẹ̀ sì di opó.
Hänen lapsensa olkoon orvot, ja hänen emäntänsä leski.
10 Jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe kiri kí wọn máa tọrọ oúnjẹ jìnnà sí ibi ahoro wọn.
Käykään hänen lapsensa kulkiana, ja kerjätkään, ja etsikään elatuksensa köyhyydessänsä.
11 Jẹ́ kí alọ́nilọ́wọ́gbà kí ó mú ohun gbogbo tí ó ní jẹ́ kí àlejò kí o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.
Kaikki mitä hänellä on, korkorahainen ottakoon, ja muukalaiset repikään hänen hyvyytensä.
12 Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan ṣe àánú fún un tàbí kí wọn káàánú lórí àwọn ọmọ rẹ̀ aláìní baba.
Älköön kenkään hänelle hyvää tehkö, eikä yksikään armahtako hänen orpojansa.
13 Kí a gé àrọ́mọdọ́mọ rẹ̀ kúrò kí orúkọ wọn kí ó parẹ́ ní ìran tí ń bọ̀.
Hänen sukunsa olkoon hävitetty: heidän nimensä olkoon toisessa polvessa pyyhitty pois.
14 Kí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba rẹ̀ kí ó wà ní ìrántí ní ọ̀dọ̀ Olúwa. Má ṣe jẹ́ kí a yọ ẹ̀ṣẹ̀ ìyá wọn kúrò.
Hänen isäinsä pahat teot tulkaan muistoksi Herran edessä, ja hänen äitinsä synti ei pidä pyyhittämän pois.
15 Jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ wọn kí ó wà ní ìrántí níwájú Olúwa kí ó lè gé ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Olkoon ne alati Herran kasvoin edessä, ja hukkukoon heidän muistonsa maan päältä,
16 Nítorí kò rántí láti ṣàánú, ṣùgbọ́n ó ṣe inúnibíni sí ọkùnrin tálákà àti olùpọ́njú, kí ó lè pa oníròbìnújẹ́ ọkàn.
Ettei hänellä ensinkään laupiutta ollut, vaan vainosi raadollista ja köyhää, ja murheellista tappaaksensa.
17 Ó fẹ́ràn láti máa mú ègún wá sí orí rẹ̀: bi inú rẹ̀ kò ti dùn si ìre, bẹ́ẹ̀ ni kí ó jìnnà sí.
Ja hän tahtoi kirousta, sen myös pitää hänelle tuleman: ei hän tahtonut siunausta, sen pitää myös hänestä kauvas erkaneman.
18 Bí ó ti fi ègún wọ ará rẹ̀ láṣọ bí ẹ̀wù bẹ́ẹ̀ ni kí ó wá sí inú rẹ̀ bí omi.
Ja hän puki kirouksen päällensä niinkuin paitansa ja se meni hänen sisällyksiinsä niinkuin vesi, ja hänen luihinsa niinkuin öljy.
19 Jẹ́ kí ó rí fún un bí aṣọ tí a dà bò ó ní ara, àti fún àmùrè tí ó fi gba ọ̀já nígbà gbogbo.
Se olkoon hänelle niinkuin vaate, jolla hän itsensä verhottaa, ja niinkuin vyö, jolla hän aina itsensä vyöttää.
20 Èyí ni èrè àwọn ọ̀tá mi láti ọwọ́ Olúwa wá; àti ti àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ibi sí ọkàn mi.
Aivan näin tapahtukoon heille Herralta, jotka ovat minua vastaan, ja puhuvat pahoin minun sieluani vastaan.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ, ìwọ ṣe fún mi Olúwa Olódùmarè, ṣe rere fún mi nítorí orúkọ rẹ. Nítorí tí àánú rẹ dára, ìwọ gbà mí.
Mutta sinä, Herra, Herra, tee minun kanssani sinun nimes tähden; sillä sinun armos on hyvä, pelasta minua.
22 Nítorí pé tálákà àti aláìní ni mí, àyà mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
Sillä minä olen köyhä ja raadollinen: minun sydämeni on särjetty minussa.
23 Èmi ń kọjá lọ bí òjìji tí àṣálẹ́, mo ń gbọ̀n sókè bí eṣú.
Minä menen pois niinkuin varjo, koska se kulkee pois, ja pudistetaan ulos niinkuin kaskaat.
24 Eékún mi di aláìlera nítorí àwẹ̀ gbígbà ẹran-ara mi sì gbẹ nítorí àìlera mi.
Minun polveni ovat heikoksi tulleet paastosta, ja minun lihani on laihtunut lihavuudesta.
25 Mo dàbí ẹ̀gàn fún àwọn olùfisùn mi; nígbà tí wọn wò mí, wọ́n gbọn orí wọn.
Ja minun täytyy olla heidän pilkkansa: koska he minun näkevät, niin he päätänsä pudistavat.
26 Ràn mí lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run mi; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
Auta minua, Herra minun Jumalani: auta minua sinun armos perästä,
27 Jẹ́ kí wọn mọ̀ pé ọwọ́ rẹ ni èyí wí pé ìwọ, Olúwa, ni ó ṣe é.
Että he tuntisivat sen sinun kädekses, ja että sinä Herra sen teet.
28 Wọ́n ó máa gégùn ún, ṣùgbọ́n ìwọ máa súre, nígbà tí wọn bá dìde kí ojú kí ó tì wọ́n, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ yóò yọ̀.
Koska he sadattavat, niin siunaa sinä: koska he karkaavat minua vastaan, niin tulkoon he häpiään, mutta sinun palvelias iloitkaan.
29 Jẹ́ kí a wọ àwọn ọ̀tá mi ní aṣọ ìtìjú kí á sì fi ìdàrúdàpọ̀ bọ̀ wọ́n lára bí ẹ̀wù.
Olkoon minun vainolliseni häväistyksellä puetut, ja olkoon häpiällänsä verhotetut niinkuin hameella.
30 Pẹ̀lú ẹnu mi èmi yóò máa yin Olúwa gidigidi ní àárín ọ̀pọ̀ ènìyàn èmi yóò máa yìn ín.
Minä kiitän suuresti Herraa suullani, ja ylistän häntä monen seassa.
31 Nítorí ó dúró ní apá ọ̀tún aláìní láti gbà á lọ́wọ́ àwọn tí ń dá ọkàn rẹ̀ lẹ́bi.
Sillä hän seisoo köyhän oikialla kädellä, auttamassa häntä niistä, jotka hänen sieluansa tuomitsevat.

< Psalms 109 >